Ọkùnrin Orí Àgbélébùú Àárín: Ètò Bíbélì Ọlọ́jọ́ Méje Tí ÀjíndeÀpẹrẹ

The Man on the Middle Cross: A 7-Day Easter Reading Plan

Ọjọ́ 1 nínú 7

ÌLÉRÍ PÁRÁDÍSÈ

“Ó sì wí pé, “Jesu, rántí mi nígbà tí ìwọ bá dé ìjọba rẹ.”Jesu sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Lónìí ni ìwọ ó wà pẹ̀lú mi ní Párádísè!’” LUKU 23:42-43 (YCB)

A kan Jésù mọ́ àgbélébùú ní àárin àwọn ọ̀daràn méjì tí wọ́n dá ní ẹ̀bi—àwọn ọ̀daràn náà sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Kristi, síbẹ̀ ìdáhùn wọn yàtọ̀ sí ara wọn. Ẹni àkọ́kọ́ tí ó ń kú náà ka àgbélébùú sí ohun tí ó tako ara rẹ̀. Ó gbàgbọ́ wí pé nítorí Jésù wà ní orí àgbélébùú, Jésù kì í ṣe Olùgbàlà. Nítorí náà, ó fi ọkùnrin tí ó wà ní àárín àgbélébùú náà ṣe yẹ̀yẹ́: “Àti ọ̀kan nínú àwọn arúfin tí a gbé kọ́ ń fi ṣe ẹlẹ́yà wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Kristi, gba ara rẹ àti àwa náà là.” (Luku 23:39). Ṣùgbọ́n ọkùnrin kejì rí àgbélébùú náà gẹ́gẹ́ bíi ìmúṣẹ. Ó mọ̀ pé nítorí pé Jésù wà ní orí àgbélébùú, òun ni Olùgbàlà.

Ọ̀daràn tí ó jẹ́ òǹrorò tẹ́lẹ̀ rí yìí ti rí Jésù ó sì ti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ìkẹyìn rẹ̀ láti mọ̀ pé Jésù kò jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kankan. Ẹ̀mí Mímọ́ sì ti la ojú rẹ̀ l'áti mọ̀ pé ìṣòro rẹ̀ pọ̀ ju bí ó ṣe rò tẹ́lẹ̀. Kì í ṣe pé wọ́n ń fì ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jẹ ẹ́ ní ọ̀nà tí ó tọ́ nìkan, àmọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ á máa bá a lọ títí ayérayé bí kò bá rí ìdáríjì gbà, èyí tí Jésù sọ nípa rẹ̀.

Lẹ́yìn tí ọkùnrin tí wọ́n dájọ́ ikú fún yìí ti rí i pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ yìí, ó bẹ Jésù tìrẹ̀lẹ̀ tìrẹ̀lẹ̀ fún ohun tí ó mọ̀ wí pé kò tọ́ sí òun: “Jesu, rántí mi ní ìgbà tí ìwọ bá dé ìjọba rẹ.” Ó ṣeé ṣe kí ó jẹ́ pé ó ti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹ̀rí náà, tí ó sì ti parí èrò sí pé, Bí ọkùnrin yìí bá jẹ́ mèsáyà, á jẹ́ ọba tí a ti ṣe ìlérí tipẹ́tipẹ́. Bí ó bá jẹ́ pé Òun ni Ọba náà, ní ìgbà náà yóò ní ìjọba kan—ìjọba ayérayé ti Ọlọ́run. Ní ìgbà tí Ó bá sì dé ìjọba Rẹ̀, bóyá ó lè rántí mi.

Ìdáhùn Jésù jẹ́ ìyanu: “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, lónìí ni ìwọ ó wà pẹ̀lú mi ní Párádísè.” Kì í ṣe pé Jésù ṣe ìlérí pé ọkùnrin yìí—àní ọkùnrin yìí— yóò lọ sí ọ̀run nìkan, ṣùgbọ́n Ó tún t'ẹnu mọ́ bí ó ṣe tètè wáyé tó: “lónìí”! A lè fi ọkàn ya àwòrán wọn bí wọ́n ti n parí ìjíròrò wọn, kìí ṣe ní orí àgbélébùú ní Kálífárì, ṣùgbọ́n ní ìjókòó ní ìjọba Ọlọ́run.

Ọ̀daràn yìí kò fún Ọba ní nǹkankan, ó sì béèrè fún ohun gbogbo. Ó sì gbà. Kò yẹ kí èyí máà kọ wá ní ominú, kí ó sì fi wá ní ọkàn balẹ̀, nítorí pé ipò tí ọ̀daràn yẹn wà ni àwa náà wà. Kò sí ohun tí a lè mú wá fún Jésù, bí ẹni pé àwọn ohun tí a ṣe lè jẹ́ kọ́kọ́rọ́ tí ó máa jẹ́ kí á wọ ìjọba Rẹ̀. Gbogbo ohun tí a mú wá ni ohun tí ọ̀daràn náà mú wá: ẹ̀ṣẹ̀ wa. ṣùgbọ́n ìdí nìyí tí a fi kan Jésù mọ́ àgbélébùú: kí àwa lè mú ẹ̀ṣẹ̀ wa tọ̀ Ọ́ wá kí Òun lè gbé e, kí Ó sì rù ú. Ìdí nìyẹn tí ìlérí tí Jésù ṣe fún ọ̀daràn náà fi jẹ́ ìlérí Rẹ̀ fún gbogbo onígbàgbọ́ tí ó bá kú: "Lónìí ni ìwọ yóò wà pẹ̀lú mi ní Párádísè.” Jẹ́ kí ìmọ̀ yẹn jẹ́ ayọ̀ rẹ àti ohun tí ó ń fún ọ ní okun láti máa yin Ọlọ́run ní ònì yìí. Ní ọjọ́ kan, ìwọ pàápàá yóò wà pẹ̀lú Ọba rẹ ní Párádísè.

  • Báwo ni Ọlọ́run ṣe ń pè mí láti ronú ní ọ̀nà mìíràn?
  • Báwo ni Ọlọ́run ṣe ń tún ọkàn mi ṣe—ohun tí mo fẹ́ràn?
  • Kí ni Ọlọ́run ń pè mí láti ṣe bí mo ṣe ń ṣe iṣẹ́ ọjọ́ mi ní òní yìí?

Ìwé mímọ́

Nípa Ìpèsè yìí

The Man on the Middle Cross: A 7-Day Easter Reading Plan

Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo ènìyàn ni ó gbà pé ayé yìí ti di ìdíbàjẹ́. Àmọ́ tí ọ̀nà àbáyọ bá wà nkọ́? Ètò àjínde ọlọ́jọ́ méje yìí bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìrírí àrà ọ̀tọ̀ tí olè orí àgbélébùú, ó sì ṣe àgbéyẹ̀wò ìdí tí ìdáhùn tòótọ́ kan ṣoṣo sí ìdíbàjẹ́ fi wà ní inú pípa ọkùnrin aláìsẹ̀ kan: ìyẹn Jésù, Ọmọ Ọlọ́run.

More

A mú ìfọkànsìn láti inú ‘Truth For Life,’ ìwé ìfọkànsìn ojoojúmọ́ tí Alistair Begg kọ, tí The Good Book Company sì tẹ̀ jáde, thegoodbook.com. Truth For Life lò ó pẹ̀lú àṣẹ. Àṣẹ-Olóhun (C) 2022, The Good Book Company. Fún àlàyé síi, jọ̀wọ́ lọ sí: https://tfl.org/365