Tún Ọkàn Rẹ Tò: Ọjọ́ 10 Láti Ba Ẹ̀ṣẹ̀ JàÀpẹrẹ

Ọlọ́run Fẹ́ Ọkàn Rẹ
Kíni Ọlọ́run fẹ́? Kí ló ń fẹ́ lọ́dọ̀ wa? Ṣé ó ń wá orin lọ́jọ́ ìsinmi tàbí àdúrà àtokànwá lóru. Gbogbo wá mọ ìdáhùn náà pé kò rí bẹ́ẹ̀. Ọlọ́run fẹ́ ọkàn wa.
Ọ̀kan lára àwọn àkókò tó ṣe kedere jù lọ nínú Bíbélì tí a ti kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ yìí ni nínú Àìsáyà. Ọlọ́run tipasẹ̀ wòlíì Rẹ̀ ṣàpèjúwe ìsàgatì kan tó ń bọ̀ wá sórí Jerúsálẹ́mù.
Bí ó ti wù kí ó rí, bí ó ti wù kí àwọn ènìyàn náà ti gbọ́ ọ̀rọ̀ Àìsáyà àti ìṣípayá Ọlọ́run tó, wọn kì yóò fetí sílẹ̀ ní òtítọ́. Wọn yóò dà bí ẹni tí a fún ní ìwé ṣùgbọ́n tí kò lè ṣí àti bí ẹni tí a fún ní ìwé ṣùgbọ́n tí kò lè kà (29:11-12).
Nítorí náà kíló fa ìjìyà tí ń bọ̀ yíì? Àti kílódé tí àwọn paádé kò le lóye àwọn ìran àti àwọn ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run?
Èyí ni ibi tí a ti rí i ní kedere ohun tí Ọlọ́run fẹ́. Ìdí nìyí.
“Nítorí àwọn ènìà yí fi ẹnu wọn súnmọ́ mi, nwọn sì fi ète wọn bu ọlá fún mi, nígbàtí ọkàn wọn jìnà sí mi” (29:13).
Ọlọ́run ń fìyà jẹ àwọn èèyàn rẹ̀, ó sì ń fọ́ wọn lójú nítorí pé wọ́n ń ṣe àṣefihàn ìsìn, àmọ́ ọkàn wọn kò sí nínú rẹ̀. Wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì fi ìyìn fún un, wọ́n sì ń sọ gbogbo ọ̀rọ̀ títọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò ní èyí tí ó ṣe kókó jù lọ – ọkàn wọn.
Ọlọ́run fẹ ọkàn rẹ, ète rẹ ko. Ó fẹ́ ìfẹ́, ìtara, ìfọkànsìn àti ìfẹ́ tó gbòòrò. Ọlọ́run fẹ́ àwọn tí wọ́n ní ìfẹ́ sí. Kò sì ní tẹ́ ẹ lọ́rùn títí tí yóò fi rí wọn.
Kí nìdí? Nítorí ó mọ̀ pé nígbà tí o bá fẹ́ Òun nìkan ni ìwọ yóò máa fẹ́ ohun rere. Ìwọ á fẹ́ ohun tí ó dara, kódà kí ṣe ohun tó dára nìkan, ṣùgbọ́n èyí tó tún dára jùlọ. Ọlọ́run fẹ́ àwọn ìfẹ́ rẹ nítorí pé ó fẹ́ irẹ fún ọ.
Àti pé báwo ni yóò ṣẹ gba ọkàn rẹ? Tóò, báwo ló ṣe ní lọ́kàn láti borí ọkàn àwọn èèyàn rẹ̀ aláìgbọràn nígbà ayé Aísáyà?
Òun yóò ṣẹ àwọn ohun ìyanu (29:14). Ṣùgbọ́n àwọn ohun ìyanu wọ̀nyí kò lẹ́ wà. Wọ̀nyí ni ohun tí ó mú ìyanu wá. Àwọn nǹkan bíi ìjìyà àti àwọn ìṣe ìdájọ́ ńlá. Ìdí tí àwọn ènìyàn fi ń fi ètè wọn sún mọ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n tí kì í ṣe ọkàn wọn ni nítorí pé wọn kò bẹ̀rù Ọlọ́run ní tòótọ́. Ó jẹ́ “májẹ̀mú tí àwọn ènìyàn fi kọ́ni” (29:13).
Nítorí náà, Ọlọ́run máa gbin ìbẹ̀rù tòótọ́ sínú ọkàn wọn. Èyí le dàbí ohun líle, ṣùgbọ́n Ọlọ́run fẹ́ ọkàn wọn. Nítorí náà òun yóò fi ara rẹ̀ hàn wọ́n ní ọ̀nà kanṣoṣo tí yóò yí wọn padà.
Ọlọ́run n yí ọkàn padà lọ́nà kan náà àní lónìí pàápàá. Ó fi ara Rẹ̀ hàn wá lọ́nà àgbàyanu. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, ọ̀nà tí ó gbà fiyè sí jù lọ nínú èyí tí ó ti fi ara Rẹ̀ hàn fún wa pẹ̀lú jẹ́ nípasẹ̀ ìdájọ́ àti ìjìyà. Ṣùgbọ́n ní àkokò yii, ìdájọ́ àti ìjìyà kò wá sórí àwa tí ó tọ́ sí. Ìbínú Ọlọ́run wá sórí Jésù, ẹni tó fara da ìyà wa bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò tọ́ sí i
Ṣé ọkàn rẹ jìnnà sí Ọlọ́run bó tilẹ̀ jẹ́ pé ètè rẹ sún mọ́ ọn? Ṣé o fẹ́ yí ìyẹn padà? Wo Jésù! wòó bí Ọlọ́run ti fi ara Rẹ̀ hàn ọ́ nínú Krístì! Jẹ́ kí ìbẹ̀rù àti ìfẹ́ Ọlọ́run wo inú ọkàn rẹ̀ nípa wíwà jinlẹ̀ sínú òtítọ́ ti Ìhìn Rere.
Ìwé mímọ́
Nípa Ìpèsè yìí

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Kristiẹni gbàgbọ́ pé ọ̀nà kan ṣoṣo láti borí ẹ̀ṣẹ̀ ni láti fi ara mọ́-ọn kí a sì má ṣubú sí inú ìdánwò. Ṣùgbọ́n ìwọ kò lè fi ọkàn rẹ ja ẹ̀ṣẹ̀; o gbọ́dọ̀ fi ọkàn rẹ jà á. Ètò ọjọ́ mẹ́wàá yìí da l'órí ìwé Rewire Your Heart, ó sì wo díẹ̀ nínú àwọn ẹsẹ̀ tí ó pàtàkì jù lọ nípa ọkàn rẹ tí yoo ràn ọ́ l'ọ́wọ́ l'áti ṣe àwárí bí o ṣe lè k'ojú ẹ̀ṣẹ̀ nípa gbígba Ìhìnrere ní ààyè láti tún ọkàn rẹ ṣe.
More