OHUN KANÀpẹrẹ

ONE THING

Ọjọ́ 2 nínú 7

Sáàmù 27:4 Ṣe àkójọ àwọn kókó pàtàkì kan tí ó máa ràn wá lọ́wọ́ nígbèésí ayé wa, èyí tí ó máa jẹ́ ká lè máa ṣe nǹkan ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì nínú ayé tí ó ń yára kánkán yìí.

Ohun àkọ́kọ́ ni pé ka BÉÈRÈ.

BÁWO la ṣe máa béèrè?

LỌ́WỌ́ ta la tí lè BÉÈRÈ?

KÍNÍ ó yẹ kí á BÉÈRÈ fún?

Mo gbà gbọ́ pé Ọlọ́run ń gbọ́ àdúrà wa, gbogbo wọn. Kì í fí ìgbà gbogbo dáhùn wọn lọ́nà tá a fẹ́. Nígbà míì, a máa ń ṣi àdúrà gbà. Àdúrà onímọtara-ẹni-nìkan la máa ń gbà tí wọn ò sì ní ète ayérayé kankan.

‌NT Wright sọ wí pé: 'Ṣùgbọ́n, fún èyí tó pọ̀ jù lọ nínú wa, ìṣòro náà kì í ṣe pé a ti ń hára gàgà láti béèrè àwọn nǹkan tí kò tọ́. Ìṣòro náà ni pé a ò fi gbogbo ara béèrè ohun tó tọ́.'

Bíbélì fi kọ́ wa, ó sì tẹnu mọ́ pé, kí á máa BÉÈRÈ.

Ìwé Ẹ́sítérì sọ ìtàn nípa bí wọ́n ṣe fi ìgboyà béèrè ohun kan . Ayaba kan wọ yàrá ìtẹ́ ọba láìgbàṣẹ. Ṣùgbọ́n ó wọlé. Ọba náà kò fi ojú rere hàn sí i nìkan, ó tún fún un ní ohun tó béèrè.

A gbọ́dọ̀ kọ bí á ṣe lè gbàdúrà sí Ọlọ́run. Ìgboyà, ẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀, a mọ̀ pé ilé Ọlọ́run ni, kì í ṣe tiwa, a sì mọ àwọn òfin tó yẹ ká tẹ̀ lé. Ohun tá a máa kọ́ nínú àpilẹ̀kọ yìí á jẹ́ ká mọ bá a ṣe lè gbàdúrà sí Ọlọ́run:

SÚN MỌ́ -Ẹ wá síwájú rẹ̀

JẸ́WỌ́ - Mú ọkàn rẹ mọ́, kó o sì tọrọ ìdáríjì

‌DÁRÍJÌ -Àwọn mìíràn

‌ÌJỌSÌN - Máa lo àkókò rẹ láti máa yin orúkọ Rẹ̀ lógo kó o sì máa gbé e ga (ìyìn, ijuba, ìdúpẹ́)

BÉÈRÈ - Ète Ìjọba Náà ('Kí ìjọba Re dé')

‌BÉÈRÈ - Ìdàgbàsókè Ara Ẹni ('Yọ́ mí bí a ti yọ́ wúrà')

‌ṢALAGBÀWÍ - Ìtọrọ, àìní, ìdílé, àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà, àwùjọ, àti àwọn ìbéèrè pàtó

‌ṢÀṢÀRÒ - Nípa Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run

‌ÌDÚPẸ́ - Yin Ọlọ́run fún gbogbo ohun tó ti ṣe àtàwọn ohun tó ṣì máa ṣe

Èyí jẹ́ ọ̀nà tó dára gan-an láti sún mọ́ Ọlọ́run, nítorí pé ó fi hàn pé Ọlọ́run ṣe pàtàkì ju ohun tá a béèrè lọ.

Lára àwọn ohun tá a lè béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run:

-Àwọn Orílẹ̀-Èdè

- Ọgbọ́n

- Ìwòsàn

- Ìdáríjì

- Ìdáǹdè

-Òmìnira nínú àníyàn

- Ìfẹ́ Ọlọ́run ni kí o ṣe

Edward Marbury sọ wí pé, 'Éni kan kò lè ní ìgbàgbọ́ láì béèrè, bẹ́ẹ̀ ni kò lè béèrè fún un láìní ìgbàgbọ́.'

Àdúrà tí a kò bá gbà kò lè gba ìdáhùn.

Kí ni a ń béèrè lọ́wọ́ Olúwa? nítorí pẹ́ ó YẸ ká béèrè.

Nípa Ìpèsè yìí

ONE THING

A máa ri ohun tí ó túnmọ̀ sí láti gbé fún Jésù nínú ayé tí kò ní àfojúsùn. Ayé yìí n sáré, a sì ní ìròyìn ní àtẹ́lẹwọ́ wa ju bí a ṣe nílo lọ. Njẹ́ ìwà ayé tuntun yìí rèé? Báwo ni a ṣe lè rìn jẹ́jẹ́ ní ayé tí ó ń sáré yìí? Sáàmù 27:4 ní ìdáhùn – OHÙN KAN, pẹ̀lú Ps Andrew Cartledge.

More

A fẹ́ dúpẹ́ lọ́wọ́ ìjọ Harvest Church fún ìpèsè ètò yìí. Fún àlàyé díẹ̀ síi, jọ̀wọ́ lọ sí https://www.harvestchurch.org.au/onething