Ìgbanájẹ: Ìtọ́sọ́nà tí ó Rọrùn fún Àdúrà ÌgboyàÀpẹrẹ

Ignited: A Simple Guide for Bold Prayer

Ọjọ́ 5 nínú 6

Ọ̀nà Mẹ́fà Láti Gbàdúrà

Bí o bá ṣe ìwádìí lórí ayélujára nípa "bí a ṣe ń gbàdúrà,” ìwọ yíó rí ọgọgọ́rọ̀rùn, bí kìí bá ṣe ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀, èrò, ìṣe, àti ìlànà nípa àdúrà. Kò sí ọ̀nà kan pàtó tí a fi ń gbàdúrà, ṣùgbọ́n àwọn ìtọ́sọ́nà wà tí ó lè ràn ọ́ lọ́wọ́:

Gbàdúrà ní Àwọn Àkókò tí Ó ti là K'alẹ̀ àti Lójú-ẹsẹ̀

Ó ṣe pàtàkí láti ní àwọn àkókò ìyàsọ́tọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run àti àwọn àsìkò ojú-ẹsẹ̀. Ìwe-mímọ́ gbà wá ní ìyànjú láti gbàdúrà láì sinmi (1 Tẹsalóníkà 5:17). Ní ìgbàkúùgbà, ní ibikíbi tí o bá ti lè ṣe bẹ́ẹ̀, gbàdúrà!

Dá Nìkan Gbàdúrà àti Pẹ̀lú Àwọn Ẹ́lòmíràn

Ní ìgbà tí ó bá nira láti gbọ́ ohùn Ọlọ́run, a máa ṣe ìrànwọ́ láti ní àwọn ọ̀rẹ́ tí ó lè gbàdúrà pẹ̀lú wa. Ní inú Bíbélì, a rí Ọlọ́run tí Ó bá àwọn ènìyàn pàdé lọ́kọ̀ọ̀kan nínú àdúrà (Mátíú 6:6), bí wọn ṣe ń gbàdúrà papọ̀ (Mátíú 18:20), àti ní àgbáríjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìjọ (Ìṣe Àpóstélì 2:42).

Gbàdúrà Jẹ́jẹ́ àti S'ókè Lálá

Sọ àwọn ọ̀rọ̀ àdúrà rẹ jàde s'íta, kódà ní ìgbà tí o bá ń dá gbàdúrà. Ó lè jọ ìjíròrò, ìwọ yíó sì ní ìsopọ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ rẹ bí ó ṣe ń rónu nípa wọn, tí ò ń sọ wọn jáde, tí o sì ń gbọ́ wọn.

Gbàdúrà Pẹ̀lú Ọkàn àti Ara Rẹ

Nínú Bíbélì, a rí àpẹẹrẹ àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbàdúrà ní ìdojúbọlẹ̀, ní eekún wọn, ní ìjókòó, ní ìnàró, tàbí pẹ̀lú ọwọ́ wọn ní gbígbé s'ókè. Yíyí ara padà lè ràn wá lọ́wọ́ láti wà lójú ìṣe kí a sì ní ìsopọ̀ mọ́ Ọlọ́run nínú àdúrà.

Gbàdúrà Pẹ̀lú Ọ̀rọ Tìrẹ àti Ti Àwọn Ẹlòmíràn

Ní ìgbà míràn, àdúrà jẹ́ ìtújáde ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ èrò àti ìfẹ́ ọkàn wa bí a ti ń ṣe tú wọn jáde fún Baba; ṣùgbọ́n nínú gbogbo ìtàn ìjọ, àwọn onígbàgbọ́ ti gba àdúra tí a kọ láti ọwọ́ àwọn ẹlòmíràn (tí à ń pé ní ìsìn). Gbígbà àwọn Sáàmù ní àdúrà tàbí àdúrà Olúwa jẹ́ àpẹẹrẹ èyí nínú Bíbélì.

Gbàdúrà Bí O Ṣe Ń Mí

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ pè é ní “àdúrà èémí”, èyí ni ìṣe tí a gbé k'alẹ̀ láti ràn wá lọ́wọ́ ní fífi ojú sun àwọn ìpele-ìpele òtítọ́ kan nínú Bíbélì: ọ̀kan ní mímí s'ínú, èkejì ní mímí s'óde, kí a sí fi ìyókù s'ílẹ̀ fún Ẹ̀mímímọ́ látí kún un gẹ́gẹ́ bí Ó ti ṣe ìlérí (Róòmù 8:26).

Àdúrà:

  • Mo gbàgbọ́ (mí s'ínú). Ran àìgbàgbọ́ mi lọ́wọ́ (mí s'óde).
  • O wà pẹ̀lú mi lọ́wọ́lọ́wọ́ (mí s'ínú). O ṣeun (mí s'óde).
  • Mo dàbí ẹni àìrí (mí s'ínú). O ṣeun nítorí pé O rí mi (mí s'óde).
  • Ìwọ ni O dá ara mi (mí s'ínú). Èmi yíó bù ọlà fún un, èmi yíó sì ṣe ìkẹ́ rẹ̀ (mí s'óde).
  • Èyí kò rọrùn (mí s'ínú). Èmi yíó dúro láti rí ọwọ́ Rẹ nínú rẹ̀, Olúwa (mí s'óde).

Nípa Ìpèsè yìí

Ignited: A Simple Guide for Bold Prayer

Àdúrà jé ẹ̀bùn, ànfàní nlá láti ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú Bàbá wa lọ́run. Nínú ètò ọlọ́jọ́ mẹ́fa yìí, a ó ṣe àwárí ohun tí Jésù kọ́ wa nípa àdúrà àti a ó sì ṣí ọkàn wa payá láti gbàdúrà lóòrèkóòrè àti pẹ̀lú ìgboyà nlá.

More

A fẹ́ dúpẹ́ lọ́wọ́ Christine Caine - A21, Propel, CCM fún ìpèsè ètò yìí. Tó bá fẹ́ mọ̀ sí, lọ sí https://www.propelwomen.org