Wíwàásù Jesu Pẹ̀lú ÌgboyàSample

Ìgboyà Láti Bẹ̀rẹ̀
Gẹ́gẹ́ bí ọmọ-ẹ̀yìn Jesu, mo fẹ́ràn láti múrasílẹ̀ àti láti ṣetán nígbà tí mob á ní àǹfààní láti ṣàlàyé ìrètí tí mo ní nínú Rẹ̀. Gbà mí gbọ́, o kò nílò láti jẹ́ onímọ̀ Bíbélì. Èmi pàápàá kì í ṣe é. Ìyẹn báyẹn, níní ìfẹ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run dájúdájú máa ràn ọ́ lọ́wọ́ nígbà tí o bá ń wàásù fún àwọn ènìyàn. Bíbélì kún fún àwọn ìtàn ìtàkurọ̀sọ láàrin àwọn ènìyàn. Èyí ń ṣe àfihàn pé Bíbélì lè tọ́ka wọn sí, ó sì lè so wọ́n pọ̀ mọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kí wọ́n lè bẹ̀rẹ̀ sí ní lò wọ́n gẹ́gẹ́ bí atọ́nà fún ayé wọn.
Lọ́pọ̀ ìgbà kí n tó bẹ̀rẹ̀ sí ní ka ìtàn inú Bíbélì fún ẹnìkan, mo fẹ́ gbọ́ ìtàn ayé ẹni náà. Ó rọrùn láti ro èrò nípa ìtàn ẹnìkan nítorí pé gbogbo wa ní ìtàn. Mo ti ṣe àwárí èyí láti jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ tó dára jùlọ. Pípààrọ̀ ìtàn kì í kàn ṣe àsìkò ẹ̀sìn tó yanu, nítorí pé a tilẹ̀ ti máa ń sọ ìtàn ayé wa lójoojúmọ́ nígbàkúùgbà àti níbikíbi tí àwọn ènìyàn bá tin í ìbápàdé pẹ̀lú ara wọn.bí o ṣe ń di ọlọ́kàn iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí i, wà á fẹ́ kí ìtàn rẹ darí lọ sínú ìtàn Ọlọ́run.
Kín ni èrèdí títẹ́tí sí ẹnìkan? Bóyá nítorí pé ó ní ìtàra fún ẹni bẹ́ẹ̀, bí Jesu tin í ìtara fún wa. Ó wá láti wá kiri àti láti gbàlà. Ìkẹ́ ni ó bẹ̀rẹ̀ ìrìn-àjò náà. Nígbà tí a bá síwọ́ ìkẹ́ fún ènìyàn, tàbí tí a bá ń ṣìkẹ́ àwọn kan nìkan, a ti yapa kúrò nínú iṣẹ́-ìránṣẹ́ Jesu. Lọ́jọ́ tí ayé wa bá wá sí òpin, àwọn tí a bá ti fọwọ́ tọ́ tí a sì ní àsopọ̀ mọ́ nìkan ni yóò nítumọ̀ jùlọ. Òtítọ́ máa ń jẹ jáde nígbà tí a bá lọ síbi ìsìnkú ẹnìkan. Ohun tí wọ́n sọ, ohun tí wọn kò sọ, àti ẹni tí ó wá bínú àti ẹni tí ó wá ṣe àpọ́nlé, gbogb wọn ló ń sọ irúfẹ̀ ayé tí ẹni náà gbé.
Gbogbo wa ni a ní ìtàn ìrìnàjò tiwa ní ayé. Àwọn ìtàn ìgbésí-ayé kan lágbára, àwọn kan kò fi bẹ́ẹ̀ lágbára. Tìrẹ lè y ani lẹ́nu kí ó sì lárinrin, tàbí kí ó banújẹ́ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìbàjẹ́ tàbí ìpinnu tí kò dára. Bóyá ó si jẹ́ àpapọ̀ méjéèjì. Síbẹ̀, o kò ní mọ ìtàn àwọn mìíràn àfi bí o bá bèèrè.
Fún ìdí èyí, bíbèèrè ìbéèrè ni ìpele tí ó pé jùlọ níbi tí ó yẹ kí o ti bẹ̀rẹ̀ pínpín ìgbàgbọ́ rẹ. àwọn ìbéèrè tí kò le bí i, ‘níbo ni o ti sẹ̀ wá?’ tàbí ‘Ǹjẹ́ o ní ẹbí?’tàbí ‘báwo ni ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ rẹ ṣe rí?’ jẹ́ àwọn ìbéèrè tó wọ́pọ̀ tí gbogbo wa máa ń bèrè láti bẹ̀rẹ̀ ìtàkurọ̀sọ pllú ènìyàn titun tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ pádé. Mo rí i pé bíbèèrè ìbéèrè rọrùn púpọ̀, ó sì máa ń fẹ́rẹ̀ yọrí sí òtítọ́. Níbí ni ìgbáradì wa ti lè ràn wá lọ́wọ́ láti fi èsì fún ẹnikẹ́ni tí ó bá bi wá ní èrèdí ìrètí tí a ní. Ìlànà yìí ni ó ya ìtàkurọ̀sọ ojoojúmọ́ sọ́tọ̀ sí ìtàkurọ̀sọ ìmọ̀ọ́mọ̀ṣe adálórí-ìhìnrere.
Bí a bá ń gbìyànjú láti wádìí bóyá ẹnìkan ní ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú Olúwa, a jẹ́ pé a níláti mọ bí ìbáṣepọ̀ náà ṣe ń ṣiṣẹ́. Ẹ jẹ́ ká bẹ̀rẹ̀ nípa wíwo bí a ṣe ń ṣẹ̀dá ìbáṣepọ̀ wa pẹ̀lú àwọn ènìyàn àti bí wọ́n ṣe lè gbòòrò si.
Scripture
About this Plan

Ìlànà kíkà ọlọ́jọ́-márùn-ún yìí yóò dì ọ́ ní àmùrè pẹ̀lú ìmọ̀ àti ìgboyà láti wàásù Jesu. Jẹ́ ìmọ̀lẹ̀ láàrin òkùnkùn!
More
Related Plans

You Say You Believe, but Do You Obey?

God's Book: An Honest Look at the Bible's Toughest Topics

Game Changers: Devotions for Families Who Play Different (Age 8-12)

Sharing Your Faith in the Workplace

Protocols, Postures and Power of Thanksgiving

Rebuilt Faith

24 Days to Reflect on God's Heart for Redemption

30 Powerful Prayers for Your Child Every Day This School Year

Awakening Faith: Hope From the Global Church
