HOSIA 3
3
Hosia ati Obinrin Alaiṣootọ
1OLUWA tún sọ fún mi pé: “Lọ fẹ́ aya tí ń ṣe àgbèrè pada, kí o fẹ́ràn rẹ̀, bí mo ti fẹ́ràn Israẹli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n yipada sí ọlọrun mìíràn, wọ́n sì fẹ́ràn láti máa jẹ àkàrà tí ó ní èso resini ninu.”
2Nítorí náà, mo rà á ní ṣekeli fadaka mẹẹdogun ati ìwọ̀n ọkà baali kan. 3Mo sì sọ fún un pé, “O gbọdọ̀ wà fún èmi nìkan fún ọjọ́ gbọọrọ láìṣe àgbèrè, láì sì lọ fẹ́ ọkunrin mìíràn; èmi náà yóo sì jẹ́ tìrẹ nìkan.” 4Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli yóo wà fún ọjọ́ gbọọrọ láìní ọba tabi olórí láìsí ẹbọ tabi ère, láìsí aṣọ efodu tabi ère terafimu. 5Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ Israẹli yóo pada tọ OLUWA Ọlọrun wọn, ati Dafidi, ọba wọn lọ. Wọn yóo fi ìbẹ̀rù wá sọ́dọ̀ OLUWA, wọn yóo sì gba oore rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.
Currently Selected:
HOSIA 3: YCE
Highlight
Share
Copy
Want to have your highlights saved across all your devices? Sign up or sign in
Bible Society of Nigeria © 1900/2010
HOSIA 3
3
Hosia ati Obinrin Alaiṣootọ
1OLUWA tún sọ fún mi pé: “Lọ fẹ́ aya tí ń ṣe àgbèrè pada, kí o fẹ́ràn rẹ̀, bí mo ti fẹ́ràn Israẹli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n yipada sí ọlọrun mìíràn, wọ́n sì fẹ́ràn láti máa jẹ àkàrà tí ó ní èso resini ninu.”
2Nítorí náà, mo rà á ní ṣekeli fadaka mẹẹdogun ati ìwọ̀n ọkà baali kan. 3Mo sì sọ fún un pé, “O gbọdọ̀ wà fún èmi nìkan fún ọjọ́ gbọọrọ láìṣe àgbèrè, láì sì lọ fẹ́ ọkunrin mìíràn; èmi náà yóo sì jẹ́ tìrẹ nìkan.” 4Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli yóo wà fún ọjọ́ gbọọrọ láìní ọba tabi olórí láìsí ẹbọ tabi ère, láìsí aṣọ efodu tabi ère terafimu. 5Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ Israẹli yóo pada tọ OLUWA Ọlọrun wọn, ati Dafidi, ọba wọn lọ. Wọn yóo fi ìbẹ̀rù wá sọ́dọ̀ OLUWA, wọn yóo sì gba oore rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.
Currently Selected:
:
Highlight
Share
Copy
Want to have your highlights saved across all your devices? Sign up or sign in
Bible Society of Nigeria © 1900/2010