“Nígbà tí mo gbọ́, ọkàn mi wárìrì, ó sì fò sókè ní ipò rẹ̀. Gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ń dún bí ààrá, ati ariwo tí ń ti ẹnu rẹ̀ jáde. Ó rán mànàmáná rẹ̀ sí wọn jákèjádò ojú ọ̀run, títí dé òpin ilẹ̀ ayé. Lẹ́yìn náà, a gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, ó sọ̀rọ̀ ninu ọlá ńlá rẹ̀, bí ìgbà tí ààrá bá sán, sibẹsibẹ kò dá mànàmáná dúró bí àwọn eniyan ti ń gbóhùn rẹ̀. Ohùn Ọlọrun dún bí ààrá tìyanu-tìyanu, a kò lè rí ìdí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀. Ó pàṣẹ pé kí yìnyín rọ̀ sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni òjò wẹliwẹli, ati ọ̀wààrà òjò. Ó ká gbogbo eniyan lọ́wọ́ iṣẹ́ kò, kí wọ́n lè mọ iṣẹ́ rẹ̀. Àwọn ẹranko wọ ihò wọn lọ, wọ́n dákẹ́ sibẹ, wọ́n sá pamọ́. Ìjì líle fẹ́ jáde láti inú yàrá rẹ̀, òtútù sì mú wá láti inú afẹ́fẹ́ tí ń fẹ́. Yìnyín ti inú èémí Ọlọrun wá, gbogbo omi inú odò sì dì. Ó fi omi kún inú ìkùukùu, ìkùukùu sì fọ́n mànàmáná rẹ̀ ká. Wọ́n ń yípo lábẹ́ ìtọ́ni rẹ̀, láti mú gbogbo àṣẹ tí ó pa ṣẹ, lórí ilẹ̀ alààyè. Ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi ṣẹlẹ̀, bóyá fún àtúnṣe ni, tabi nítorí ilẹ̀ rẹ̀, tabi láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
Kà JOBU 37
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 37:1-13
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò