Elihu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ bọ̀, ó ní, “Ẹ gbọ́rọ̀ mi, ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n, ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ẹ ní ìmọ̀, nítorí bí ahọ́n ti í máa ń tọ́ oúnjẹ wò, bẹ́ẹ̀ ni etí náà lè máa tọ́ ọ̀rọ̀ wò Ẹ jẹ́ kí á yan ohun tí ó tọ́, kí á jọ jíròrò ohun tí ó dára láàrin ara wa. Jobu sọ pé òun kò jẹ̀bi, ó ní Ọlọrun ni ó kọ̀ tí kò dá òun láre. Ó ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun jàre, Ọlọrun ka òun kún òpùrọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kò dẹ́ṣẹ̀, ọgbẹ́ òun kò ṣe é wòsàn. “Ta ló dàbí Jobu, tí ń kẹ́gàn Ọlọrun nígbà gbogbo, tí ó ń bá àwọn aṣebi kẹ́gbẹ́, tí ó sì ń bá àwọn eniyan burúkú rìn? Nítorí ó ń sọ pé, ‘Kò sí èrè kankan, ninu ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun.’
Kà JOBU 34
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 34:1-9
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò