JOBU 24:13-25

JOBU 24:13-25 YCE

“A rí àwọn tí wọ́n kọ ìmọ́lẹ̀, tí wọn kò mọ ọ̀nà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró ní ọ̀nà náà. Bí ilẹ̀ bá ṣú, apànìyàn á dìde, kí ó lè pa talaka ati aláìní, a sì dàbí olè ní òru. Alágbèrè pàápàá ń ṣọ́ kí ilẹ̀ ṣú, ó ń wí pé, ‘Kò sí ẹni tí yóo rí mi’; ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀. Lóru, wọn á máa lọ fọ́ ilé kiri, ṣugbọn bí ilẹ̀ bá ti mọ́, wọn á ti ìlẹ̀kùn mọ́rí, wọn kì í rí ìmọ́lẹ̀. Àárọ̀ ni òkùnkùn biribiri jẹ́ fún gbogbo wọn, ọ̀rẹ́ wọn ni òkùnkùn biribiri tí ó bani lẹ́rù.” Sofari dáhùn pé, “O sọ wí pé, ‘Ìṣàn omi a máa gbá àwọn ẹni ibi lọ kíákíá; ìpín tiwọn a sì di ìfibú ninu ilẹ̀ náà, ẹnikẹ́ni kìí sì í lọ sinu ọgbà àjàrà wọn láti ṣiṣẹ́ mọ́. Bí ọ̀gbẹlẹ̀ ati ooru ṣe máa ń mú kí omi yìnyín gbẹ bẹ́ẹ̀ ni ibojì ṣe ń gbé àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ mì. Wọn á gbàgbé wọn láàrin ìlú, ẹnikẹ́ni kì í ranti orúkọ wọn mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi ṣe é wó lulẹ̀ bí ìtì igi.’ Wọ́n ń jẹ oúnjẹ àgàn tí kò bímọ, wọn kò sì ṣe rere fún opó. Sibẹsibẹ Ọlọrun fi ẹ̀mí gígùn fún alágbára nípa agbára rẹ̀; wọn á gbéra nígbà tí ayé bá sú wọn. Ọlọrun ń dáàbò bò wọ́n, ó ń ràn wọ́n lọ́wọ́, ó sì ń pa wọ́n mọ́ ni ọ̀nà wọn. A gbé wọn ga fún ìgbà díẹ̀, lẹ́yìn náà, a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn á rọ, wọn á sì rẹ̀ dànù bí ewé, a ké wọn kúrò bí orí ọkà bàbà. Bí kò bá rí bẹ́ẹ̀, kí ẹnìkan já mi nírọ́, kí ó sì fi hàn pé ìsọkúsọ ni mò ń sọ.”