“Kí ló dé tí Olodumare kò fi yan ọjọ́ ìdájọ́, kí àwọn tí wọ́n mọ̀ ọ́n sì rí ọjọ́ náà? “Àwọn eniyan a máa hú òkúta ààlà kúrò, láti gba ilẹ̀ ẹlòmíràn kún tiwọn, wọn a máa fi ipá sọ agbo ẹran ẹlòmíràn di tiwọn. Wọn a kó kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìníbaba lọ, wọn a gba akọ mààlúù opó gẹ́gẹ́ bí ohun ìdógò. Wọn a ti àwọn aláìní kúrò lójú ọ̀nà, gbogbo àwọn talaka a sì lọ sápamọ́. “Àwọn aláìní a máa ṣe làálàá káàkiri, bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ inú aṣálẹ̀, wọn a máa wá oúnjẹ fún àwọn ọmọ wọn ninu aṣálẹ̀. Wọn a máa kó oúnjẹ jọ fún ẹran wọn ninu oko olóko wọn a sì máa he èso àjàrà ní oko ìkà. Wọn a máa sùn ní ìhòòhò ní gbogbo òru, wọn kìí sìí rí aṣọ fi bora nígbà òtútù. Òjò a pa wọ́n lórí òkè, wọn a máa rọ̀ mọ́ àpáta nítorí àìsí ààbò. (Àwọn kan ń já àwọn ọmọ aláìníbaba gbà lẹ́nu ọmú, wọ́n sì ń gba ọmọ ọwọ́ lọ́wọ́ àwọn aláìní gẹ́gẹ́ bí ohun ìdógò.) Àwọn aláìní ń rìn kiri ní ìhòòhò láìrí aṣọ wọ̀; ebi ń pa wọ́n, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìtí ọkà ni wọ́n rù. Wọ́n ń fún òróró lára èso olifi tí ó wà ní oko ìkà, òùngbẹ sì ń gbẹ wọ́n, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọtí ni wọ́n ń pọn. Àwọn tí wọn ń kú lọ ń kérora ní ìgboro, àwọn tí a pa lára ń ké fún ìrànlọ́wọ́, ṣugbọn Ọlọrun kò fetísí adura wọn.
Kà JOBU 24
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 24:1-12
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò