Job 15:14-26
Job 15:14-26 Bibeli Mimọ (YBCV)
Kili enia ti o fi mọ́? ati ẹniti a tinu obinrin bi ti yio fi ṣe olododo? Kiyesi i, on (Ọlọrun) kò gbẹkẹle awọn ẹni-mimọ́ rẹ̀, ani awọn ọrun kò mọ́ li oju rẹ̀. Ambọtori enia, ẹni irira ati elẽri, ti nmu ẹ̀ṣẹ bi ẹni mu omi. Emi o fi hàn ọ, gbọ́ ti emi, eyi ti emi si ri, on li emi o si sọ. Ti awọn ọlọgbọ́n ti pa ni ìtan lati ọdọ awọn baba wọn wá, ti nwọn kò si fi pamọ́. Awọn ti a fi ilẹ aiye fun nikan, alejo kan kò si là wọn kọja. Enia buburu nṣe lãlã, pẹlu irora li ọjọ rẹ̀ gbogbo, ati iye ọdun li a dá silẹ fun aninilara. Iró ìbẹru mbẹ li eti rẹ̀, ninu irora ni alaparun a dide si i. O kò gbagbọ pe on o jade kuro ninu okunkun; a si ṣa a sapakan fun idà. O nwò kakiri fun onjẹ, wipe, nibo li o wà, o mọ̀ pe ọjọ òkunkun sunmọ tosi. Ipọnju pẹlu irora ọkàn yio mu u bẹ̀ru, nwọn o si ṣẹgun rẹ̀ bi ọba ti imura ogun. Nitoripe o ti nawọ rẹ̀ jade lodi si Ọlọrun, o si mura rẹ̀ le lodi si Olodumare. O sure, o si fi ẹhin giga kọlu u, ani fi ike-koko apata rẹ̀ ti o nipọn.
Job 15:14-26 Yoruba Bible (YCE)
Kí ni eniyan jẹ́, tí ó fi lè mọ́ níwájú Ọlọrun? Kí ni ẹnikẹ́ni tí obinrin bí já mọ́, tí ó fi lè jẹ́ olódodo? Wò ó, Ọlọrun kò fọkàn tán àwọn angẹli, àwọn ọ̀run kò sì mọ́ níwájú rẹ̀. Kí á má tilẹ̀ wá sọ ti eniyan tí ó jẹ́ aláìmọ́ ati ẹlẹ́gbin, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bí ẹni mu omi! “Fetí sílẹ̀, n óo sọ fún ọ, n óo sọ ohun tí ojú mi rí, (ohun tí àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n sọ, tí àwọn baba wọn kò sì fi pamọ́, àwọn nìkan ni a fún ní ilẹ̀ náà, àlejò kankan kò sì sí láàrin wọn). Ẹni ibi ń yí ninu ìrora ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, àní, ní gbogbo ọdún tí a là sílẹ̀ fún ìkà. Etí rẹ̀ kún fún igbe tí ó bani lẹ́rù, ninu ìdẹ̀ra rẹ̀ àwọn apanirun yóo dìde sí i. Kò gbàgbọ́ pé òun lè jáde kúrò ninu òkùnkùn; ati pé dájú, ikú idà ni yóo pa òun. Ó ń wá oúnjẹ káàkiri, ó ń bèèrè pé, ‘Níbo ló wà?’ Òun gan-an sì nìyí, oúnjẹ àwọn igún! Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn ti súnmọ́ tòsí. Ìdààmú ati ìrora dẹ́rùbà á, wọ́n ṣẹgun rẹ̀, bí ọba tí ó múra ogun. Nítorí pé ó ṣíwọ́ sókè sí Ọlọrun, o sì ṣe oríkunkun sí Olodumare, ó ń ṣe oríkunkun sí i, ó sì gbé apata tí ó nípọn lọ́wọ́ láti bá a jà
Job 15:14-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo? Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀, mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi. “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; Èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ, ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́, Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá. Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára. Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i. Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà. Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí. Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun. Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè, Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.