Èmi ó yìn ọ́, OLúWA, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; Èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo. Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; Èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ. Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; Wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ. Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo. Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé. Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
Kà Saamu 9
Feti si Saamu 9
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Saamu 9:1-6
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò