Òwe 20:1-4

Òwe 20:1-4 YCB

Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n. Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà. Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.