“Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára: Òun ló ni ìmọ̀ àti òye. Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan. Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo. Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; Ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe. Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò, A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀. Ó tú ìdè ọba, Ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já. Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò, Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba. Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò, Ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè. Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá, Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára. Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá, Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀. Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù. Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, A sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí. Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀, Òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.
Kà Jobu 12
Feti si Jobu 12
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Jobu 12:13-25
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò