Títí gbogbo wa yóò fi dé ìṣọ̀kan ìgbàgbọ́ àti ìmọ̀ Ọmọ Ọlọ́run, títí a ó fi di ọkùnrin, títí a ó fi dé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìwọ̀n Kristi. Kí àwa má ṣe jẹ́ èwe mọ́, tí a ń fi gbogbo afẹ́fẹ́ ẹ̀kọ́ tì síwá tì sẹ́yìn, tí a sì fi ń gbá kiri, nípa ìtànjẹ ènìyàn, nípa àrékérekè fun ọgbọ́nkọ́gbọ́n àti mú ni ṣìnà; Ṣùgbọ́n ká a máa sọ òtítọ́ ní ìfẹ́, kí a lè máa dàgbàsókè nínú rẹ̀ ní ohun gbogbo ẹni tí i ṣe orí, àní Kristi.
Kà Efesu 4
Feti si Efesu 4
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Efesu 4:13-15
3 Awọn ọjọ
Kìí ṣe pé ìgbé ayé onígbàgbọ́ ní ọ̀nà kan pàtó tí ó ń gbà ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tí ó ti gba Krístì. Bí ó ti lẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ti Krístì, a ṣì wà nínú ayé yìí (Jòhánù 17:16). ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú àlàkalẹ̀ nílò ìmúyàtọ̀ tí ó mú ìdọ́gba bá wíwà wa lójúkorojú nínú ayé pẹ̀lú ìdámọ̀ wa nípa ẹ̀mí. Bíi ẹ̀dá ti ẹ̀mí, a gbọ́dọ̀ ṣe bó ti tọ́.
5 Awọn ọjọ
A pè wá sí iṣẹ́ aṣíwájú bíi Jesu. Iṣẹ́ aṣíwájú bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ara-ẹni, kìí ṣe ipò, ibi-àfẹ́dé Iṣẹ́ aṣíwájú sì jẹmọ́ ìdarí àwọn ènìyàn Ọlọrun sí ìpinnu Rẹ̀ fún ayé wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan ẹ̀kọ́-kíkà ojoojúmọ́ yìí yóò ṣèrànwọ́ láti ṣàgbékalẹ̀ ìpìlẹ̀ fífẹsẹ̀mulẹ̀ nípa ipò aṣíwájú tó ńránnilétí pé, kí o tó jẹ́ aṣíwájú, o kọ́kọ́ jẹ́ ìránṣẹ́, kí o tó jẹ́ ìránṣẹ́, o kọ́kọ́ jẹ́ àyànfẹ́ ọmọ-Ọlọrun
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò