2 Samuẹli 21:5-7

2 Samuẹli 21:5-7 YCB

Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli. Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún OLúWA ní Gibeah ti Saulu ẹni tí OLúWA ti yàn.” Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.” Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra OLúWA tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu.