Jẹ́ kí tabili oúnjẹ tí wọ́n tẹ́ fún ara wọn di ẹ̀bìtì fún wọn; kí àsè ẹbọ wọn sì di tàkúté. Jẹ́ kí ojú wọn ṣú, kí wọn má lè ríran; kí gbogbo ara wọn sì máa gbọ̀n rìrì. Rọ òjò ibinu rẹ lé wọn lórí, kí o sì jẹ́ kí wọ́n rí gbígbóná ibinu rẹ. Kí ibùdó wọn ó di ahoro, kí ẹnikẹ́ni má sì gbé inú àgọ́ wọn. Nítorí ẹni tí o ti kọlù ni wọ́n tún gbógun tì; ẹni tí o ti ṣá lọ́gbẹ́ ni wọ́n sì tún ń pọ́n lójú. Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; má sì jẹ́ kí wọ́n rí ìdáláre lọ́dọ̀ rẹ. Pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò ninu ìwé ìyè; kí á má sì kọ orúkọ wọn mọ́ ti àwọn olódodo. Ojú ń pọ́n mi, mo sì ń jẹ̀rora; Ọlọrun, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè! Èmi ó fi orin yin orúkọ Ọlọrun; n óo fi ọpẹ́ gbé e ga. Èyí yóo tẹ́ Ọlọrun lọ́rùn ju akọ mààlúù lọ, àní, akọ mààlúù tòun tìwo ati pátákò rẹ̀. Àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóo rí i, inú wọn yóo dùn; ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wá Ọlọrun, ẹ jẹ́ kí ọkàn yín sọjí. Nítorí OLUWA a máa gbọ́ ti àwọn aláìní, kì í sìí kẹ́gàn àwọn eniyan rẹ̀ tí ó wà ní ìgbèkùn. Jẹ́ kí ọ̀run ati ayé kí ó yìn ín, òkun ati gbogbo ohun tí ó ń rìn káàkiri ninu wọn. Nítorí Ọlọrun yóo gba Sioni là; yóo sì tún àwọn ìlú Juda kọ́; àwọn iranṣẹ rẹ̀ yóo máa gbé inú rẹ̀, yóo sì di tiwọn. Àwọn ọmọ àwọn iranṣẹ rẹ̀ yóo jogún rẹ̀; àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ̀ yóo sì máa gbé inú rẹ̀.
Kà ORIN DAFIDI 69
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 69:22-36
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò