ORIN DAFIDI 135:5-12

ORIN DAFIDI 135:5-12 YCE

Èmi mọ̀ pé OLUWA tóbi, ati pé ó ju gbogbo oriṣa lọ. Bí ó ti wu OLUWA ni ó ń ṣe lọ́run ati láyé, ninu òkun ati ninu ibú. Òun ló gbá ìkùukùu jọ láti òpin ilẹ̀ ayé, ó fi mànàmáná fún òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti inú ilé ìṣúra rẹ̀. Òun ló pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti, ati teniyan ati tẹran ọ̀sìn. Ẹni tí ó rán iṣẹ́ abàmì ati iṣẹ́ ìyanu sí ilẹ̀ Ijipti, ó rán sí Farao ati gbogbo àwọn iranṣẹ rẹ̀. Ẹni tí ó pa orílẹ̀-èdè pupọ run; ó pa àwọn ọba alágbára: Sihoni ọba àwọn Amori, Ogu ọba Baṣani, ati gbogbo ọba ilẹ̀ Kenaani. Ó pín ilẹ̀ wọn fún àwọn eniyan rẹ̀; ó pín in fún Israẹli bí ohun ìní wọn.