ÌWÉ ÒWE 20:1-4

ÌWÉ ÒWE 20:1-4 YCE

Ẹlẹ́yà ni ọtí waini, aláriwo ní ọtí líle, ẹnikẹ́ni tí a bá fi tànjẹ kò gbọ́n. Ibinu ọba dàbí bíbú kinniun, ẹni tí ó bá mú ọba bínú fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu. Nǹkan iyì ni pé kí eniyan máa yẹra fún ìjà, ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan níí máa ń jà. Ọ̀lẹ kì í dáko ní àkókò, nítorí náà, nígbà ìkórè, kò ní rí nǹkankan kó jọ.