Nítorí pé ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan tí ó fẹ́ yanjú owó òwò pẹlu àwọn ẹrú rẹ̀. Nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣírò owó, wọ́n mú ẹnìkan wá sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó jẹ ẹ́ ní ọ̀kẹ́ àìmọye. Kò ní ohun tí yóo fi san gbèsè yìí, nítorí náà olówó rẹ̀ pàṣẹ pé kí á ta òun ati iyawo rẹ̀, ati àwọn ọmọ rẹ̀ ati gbogbo ohun tí ó ní, kí á fi san gbèsè rẹ̀. Ẹrú náà bá dọ̀bálẹ̀, ó bẹ olówó rẹ̀ pé, ‘Ṣe sùúrù fún mi, n óo san gbogbo gbèsè mi fún ọ.’ Olówó rẹ̀ wá ṣàánú rẹ̀, ó bá dá a sílẹ̀, ó sì bùn ún ní owó tí ó yá. “Nígbà tí ẹrú náà jáde, ó rí ẹrú, ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ kan tí ó jẹ ẹ́ ní eélòó kan. Ó bá dì í mú, ó fún un lọ́rùn, ó ní; ‘San gbèsè tí o jẹ mí.’ Ẹrú, ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ bá dọ̀bálẹ̀, ó ń bẹ̀ ẹ́ pé, ‘Ṣe sùúrù fún mi, n óo san án fún ọ.’ Ṣugbọn kò gbà; ẹ̀wọ̀n ni ó ní kí wọ́n lọ jù ú sí títí yóo fi san gbèsè tí ó jẹ. Nígbà tí àwọn ẹrú, ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀, inú bí wọn pupọ, wọ́n bá lọ ro ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún olówó wọn.
Kà MATIU 18
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: MATIU 18:23-31
3 Awọn ọjọ
Ìdáríjìn jẹ́ ọ̀kan pàtàkì nínú ìgbésíayé Kristẹni fún ìbáṣepọ̀ àlààfíà àti èyí tó gbèrú pẹ̀lú Ọlọ́run àti ènìyàn. Kì í ṣe pé Jésù tún ìdáríjìn ṣàlàyé nípa ìgbéayé àti àwọn ẹ̀kọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tún pèsè oore-ọ̀fẹ́ tí a nílò láti gba ìdáríjìn àti láti dárí jin ni nípasẹ̀ Ẹ̀mí rẹ̀. Gbogbo ọmọ Ọlọ́run ni a ti fún ní agbára láti gbọ́ràn sí àṣẹ Ọlọ́run nípa dídáríjin ẹlòmíràn gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe dárí jin àwọn tìkalára wọn.
7 Days
Whether we suffer emotional or physical wounds, forgiveness is the cornerstone of the Christian life. Jesus Christ experience all kinds of unfair and unjust treatment, even to the point of a wrongful death. Yet in his final hour, he forgave the mocking thief on the other cross and his executioners.
8 Days
Join J.John on an eight-day study on the Lord’s Prayer, that incredibly profound and helpful teaching given by Jesus on how we should pray.
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò