“Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí Ọlọrun bá bá wí, nítorí náà, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olodumare. Ó ń ṣá ni lọ́gbẹ́, ṣugbọn ó tún ń dí ọgbẹ́ ẹni. Ó ń pa ni lára, ṣugbọn ọwọ́ rẹ̀ ló tún fi ń ṣe ìwòsàn. Yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ ìnira lọpọlọpọ ìgbà, bí ibi ń ṣubú lu ara wọn, kò ní dé ọ̀dọ̀ rẹ. Ní àkókò ìyàn, yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú. Ní àkókò ogun, yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ idà. Yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́gàn, o kò ní bẹ̀rù nígbà tí ìparun bá dé. Ninu ìparun ati ìyàn, o óo máa rẹ́rìn-ín, o kò ní bẹ̀rù àwọn ẹranko ìgbẹ́. O kò ní kan àwọn òkúta ninu oko rẹ, àwọn ẹranko igbó yóo wà ní alaafia pẹlu rẹ. O óo máa gbé ilé rẹ ní àìséwu. Nígbà tí o bá ka ẹran ọ̀sìn rẹ, kò ní dín kan. Àwọn arọmọdọmọ rẹ yóo pọ̀, bí ewéko ninu pápá oko. O óo di arúgbó kí o tó kú, gẹ́gẹ́ bí ọkà tií gbó kí á tó kó o wá síbi ìpakà. Wò ó! A ti wádìí àwọn nǹkan wọnyi, òtítọ́ ni wọ́n. Gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ire ara rẹ ni.”
Kà JOBU 5
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 5:17-27
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò