JOBU 41:1-11

JOBU 41:1-11 YCE

“Ṣé o lè fi ìwọ̀ fa Lefiatani jáde, tabi kí o fi okùn di ahọ́n rẹ̀? Ṣé o lè fi okùn sí imú rẹ̀, tabi kí o fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní àgbọ̀n? Ṣé yóo bẹ̀ ọ́, tabi kí ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá ọ sọ̀rọ̀? Ṣé yóo bá ọ dá majẹmu, pé kí o fi òun ṣe iranṣẹ títí lae? Ṣé o lè máa fi ṣeré bí ọmọ ẹyẹ, tabi kí o dè é lókùn fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ? Ṣé àwọn oníṣòwò lè yọwó rẹ̀? Àbí wọ́n lè pín Lefiatani láàrin ara wọn? Ṣé o lè fi ọ̀kọ̀ gún ẹran ara rẹ̀, tabi kí o fi ẹ̀sín àwọn apẹja gún orí rẹ̀? Lọ fọwọ́ kàn án; kí o wo irú ìjà tí yóo bá ọ jà; o kò sì ní dán irú rẹ̀ wò mọ́ lae! “Ìrètí ẹni tí ó bá fẹ́ bá a jà yóo di òfo, nítorí ojora yóo mú un nígbà tí ó bá rí i. Ta ló láyà láti lọ jí i níbi tí ó bá sùn sí? Ta ló tó kò ó lójú? Ta ni mo gba nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀ tí mo níláti dá a pada fún un? Kò sí olúwarẹ̀ ní gbogbo ayé.