JOBU 39:13-30

JOBU 39:13-30 YCE

“Ògòǹgò lu ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ninu ọláńlá rẹ̀, ṣugbọn kò lè fò bí ẹyẹ àkọ̀? Ó yé ẹyin rẹ̀ sórí ilẹ̀, kí ooru ilẹ̀ lè mú wọn, ó gbàgbé pé ẹnìkan le tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ kí wọn sì fọ́, ati pé ẹranko ìgbẹ́ lè fọ́ wọn. Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀, ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn, kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán; nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye. Ṣugbọn nígbà tí ó bá ṣetán ati sáré, a máa fi ẹṣin ati ẹni tí ó gùn ún ṣe yẹ̀yẹ́. “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára, tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn? Ṣé ìwọ lò ń mú kí ó máa ta pọ́nún bí eṣú, tí kíké rẹ̀ sì ń bani lẹ́rù? Ó fẹsẹ̀ walẹ̀ ní àfonífojì, ó yọ̀ ninu agbára rẹ̀, ó sì jáde lọ sí ojú ogun. Kò mọ ẹ̀rù, ọkàn rẹ̀ kì í rẹ̀wẹ̀sì, bẹ́ẹ̀ ni kì í sá fún idà. Ó gbé apó ọfà sẹ́yìn, tí ń mì pẹkẹpẹkẹ, pẹlu ọ̀kọ̀ tí ń kọ mànà, ati apata. Ó ń fi ẹnu họlẹ̀ pẹlu ìgboyà ati ìwàǹwára, nígbà tí ipè dún, ara rẹ̀ kò balẹ̀. Nígbà tí fèrè dún, ó kọ, ‘Hàáà!’ Ó ń gbóòórùn ogun lókèèrè, ó ń gbọ́ igbe ọ̀gágun tí ń pàṣẹ. “Ṣé ìwọ lo kọ́ àwòdì bí a ti í fò, tí ó fi na ìyẹ́ rẹ̀ sí ìhà gúsù? Ṣé ìwọ ni o pàṣẹ fún idì láti fò lọ sókè, tabi láti tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sórí òkè gíga? Ó kọ́ ilé rẹ̀ sórí òkè gíga-gíga, ninu pàlàpálá àpáta. Níbẹ̀ ni ó ti ń ṣọ́ ohun tí yóo pa, ojú rẹ̀ a sì rí i láti òkèèrè réré. Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa mu ẹ̀jẹ̀, ibi tí òkú bá sì wà ni idì máa ń wà.”