“Fetí sílẹ̀, ìwọ Jobu, dúró kí o sì ronú nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu Ọlọrun. Ǹjẹ́ o mọ bí Ọlọrun ṣe pàṣẹ, tí ó sì mú kí mànàmáná awọsanma tàn? Ǹjẹ́ o mọ̀ bí ó ṣe so awọsanma rọ̀, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ ni; ìwọ tí ooru mú nígbà tí ayé dákẹ́ rọ́rọ́ nítorí pé afẹ́fẹ́ ìhà gúsù kò fẹ́? Ṣé o lè tẹ́ ojú ọ̀run bí ó ti tẹ́ ẹ, kí ó le, kí ó sì dàbí dígí tí ń dán? Kọ́ wa ní ohun tí a lè bá Ọlọrun sọ, a kò lè kó àròyé wa jọ siwaju rẹ̀, nítorí àìmọ̀kan wa. Ṣé kí n sọ fún Ọlọrun pé n ó bá a sọ̀rọ̀ ni? Ta ni yóo fẹ́ kí á gbé òun mì? “Ẹnikẹ́ni kò lè wo ìmọ́lẹ̀ ojú ọ̀run nígbà tí ó bá ń tàn ní awọsanma, nígbà tí afẹ́fẹ́ bá fẹ́ tí ó sì gbá wọn lọ. Láti ìhà àríwá ni Ọlọrun ti yọ, ó fi ọlá ńlá, tí ó bani lẹ́rù, bora bí aṣọ. Àwámárìídìí ni Olodumare– agbára ati ìdájọ́ òtítọ́ rẹ̀ pọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì í kọ òdodo sílẹ̀. Nítorí náà, gbogbo eniyan bẹ̀rù rẹ̀, kò sì náání àwọn tí wọ́n gbọ́n lójú ara wọn.”
Kà JOBU 37
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 37:14-24
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò