Jobu tún dáhùn pé, “Mo fi Ọlọrun tí ó gba ẹ̀tọ́ mi búra, mo fi Olodumare tí ó mú kí ọkàn mi bàjẹ́ ṣẹ̀rí, níwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè, tí mo sì ń mí, n kò ní fi ẹnu mi purọ́, ahọ́n mi kò sì ní sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn. Kí á má rí i, n kò jẹ́ pè yín ní olóòótọ́; títí di ọjọ́ ikú mi ni n óo dúró lórí ọ̀rọ̀ mi, pé mo wà lórí àre. Mo dúró lórí òdodo mi láìyẹsẹ̀, ọkàn mi kò ní dá mi lẹ́bi, títí n óo fi kú. “Kí ó rí fún ọ̀tá mi gẹ́gẹ́ bí í ti í rí fún ẹni ibi, kí ó sì rí fún ẹni tí ó dojú kọ mí bí í ti í rí fún alaiṣododo. Ìrètí wo ni ẹni tí kò mọ Ọlọrun ní nígbà tí Ọlọrun bá pa á run, tí Ọlọrun sì gba ẹ̀mí rẹ̀? Ǹjẹ́ Ọlọrun yóo gbọ́ igbe rẹ̀, nígbà tí ìyọnu bá dé bá a? Ǹjẹ́ yóo ní inú dídùn sí Olodumare? Ǹjẹ́ yóo máa ké pe Ọlọrun nígbà gbogbo?
Kà JOBU 27
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 27:1-10
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò