“Gbogbo ìwọ̀nyí ni ojú mi ti rí rí, tí etí mi ti gbọ́, tí ó sì yé mi. Ohun tí ẹ mọ̀ wọnyi, èmi náà mọ̀ ọ́n, ẹ kò sàn jù mí lọ. Ṣugbọn n óo bá Olodumare sọ̀rọ̀, Ọlọrun ni mo sì fẹ́ bá rojọ́. Ẹ̀yin òpùrọ́ ati ẹlẹ́tàn wọnyi, ẹ̀yin oníṣègùn tí ẹ kò lè wonisàn. Ẹ̀ bá jẹ́ pa ẹnu yín mọ́ ni, à bá pè yín ní ọlọ́gbọ́n! Nisinsinyii ẹ gbọ́ èrò ọkàn mi, kí ẹ sì fetísí àròyé mi. Ṣé ẹ óo máa parọ́ ní orúkọ Ọlọrun ni, kí ẹ sì máa sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní orúkọ rẹ̀? Ṣé ẹ fẹ́ máa ṣe ojuṣaaju fún Ọlọrun ni? Tabi ẹ fẹ́ jẹ́ agbẹjọ́rò rẹ̀? Ṣé ẹ óo yege bí ó bá dán yín wò? Tabi ẹ lè tan Ọlọrun bí ẹni tan eniyan? Dájúdájú, yóo ba yín wí, bí ẹ bá ń ṣe ojuṣaaju níkọ̀kọ̀. Ògo rẹ̀ yóo dẹ́rùbà yín, jìnnìjìnnì rẹ̀ yóo dà bò yín. Àwọn òwe yín kò wúlò, àwíjàre yín kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀. Ẹ dákẹ́, kí n ráyè sọ tèmi, kí ohun tí yóo bá dé bá mi dé bá mi. N óo dijú, n óo fi ẹ̀mí ara mi wéwu. Wò ó, yóo pa mí; n kò ní ìrètí; sibẹ n óo wí àwíjàre tèmi níwájú rẹ̀. Èyí ni yóo jẹ́ ìgbàlà mi, nítorí pé ẹni tí kò mọ Ọlọrun, kò ní lè dúró níwájú rẹ̀. Fetí sílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi, kí o sì gbọ́ mi ní àgbọ́yé. Wò ó, mo ti múra ẹjọ́ mi sílẹ̀; mo sì mọ̀ pé n óo gba ìdáláre. Ta ni yóo wá bá mi rojọ́? Bí ó bá wá, n óo dákẹ́, n óo sì kú.
Kà JOBU 13
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 13:1-19
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò