“Ọjọ́ ń bọ̀, tí ọkà yóo so jìnwìnnì, tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò ní lè kórè rẹ̀ tán kí àkókò gbígbin ọkà mìíràn tó dé. Ọgbà àjàrà yóo so, tóbẹ́ẹ̀ tí a kò ní lè fi ṣe waini tán kí àkókò ati gbin òmíràn tó dé. Ọtí waini dídùn yóo máa kán sílẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá, ọtí waini yóo sì máa ṣàn jáde lára àwọn òkè kéékèèké. N óo dá ire Israẹli, àwọn eniyan mi, pada, wọn yóo tún àwọn ìlú tí wọ́n ti wó kọ́, wọn yóo sì máa gbé inú wọn. Wọn yóo gbin àjàrà, wọn yóo sì mu ọtí waini rẹ̀. Wọn yóo ṣe ọgbà, wọn yóo sì jẹ èso rẹ̀.
Kà AMOSI 9
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: AMOSI 9:13-14
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò