Ètò Olúwa Fún AyéèÀpẹrẹ

God’s Plan For Your Life

Ọjọ́ 2 nínú 6

Ètò Ọlọ́run fún ayéè rẹ nííṣe pelu ẹni t'íwọ jẹ́ ju ohun t'íwọ íṣe.

Kí ni mo nílò láti ṣe? 

Ó ṣeé ṣe kí ó ti wà ìdáhùn sí ìbéèrè yìí lọ́pọ̀ ìgbà, pàápàá tí o bá ní ìpinnu pàtàkì láti ṣe, bíi ilé-ẹ̀kọ́ gíga tío máa lọ tàbí irú iṣẹ́ t'oma yàn láàyò. 

Irú ìbéèrè yí ni olórí ẹ̀sìn kan bi Jésù nínú Bíbélì: Àṣẹ wò ni ó ṣe pàtàki jùlọ nínú ìwé òfin?(Mátíù 22:36 NIV) Lọ́rọ̀ kan: kíni mo nílò láti ṣe?

Ní ẹsẹ̀ tí ó tẹ̀le, a rí èsì tí Jésù fi: “Ó gbọ́dọ̀ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn, ẹ̀mí àti èrò rẹ.” Èyí ni ó jù tí ó sì jẹ́ àkọ́kọ́ nínú òfin. Èkejì tíó tún ṣe pàtàkì: ‘Fẹ́ràn ọmọ làkejì rẹ gẹ́gẹ́ bíi ara rẹ.’ (Mátíù 22:37-39 NIV, pẹ̀lú àfikún)

Nígbà tí a bá ń gbìyànjú láti wádìí ètò Ọlọ́run fún ayéè wa, a lè bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ǹkan méjì tí Jésù ní k'áṣe yìí:

1.) Fẹ́ràn Ọlọ́run.

2.) Fẹ́ràn àwọn èèyàn bíi tìrẹ.

O lè máa gbàárò, ìyẹn kò le, ṣùgbọ́n báwo ni màáṣe mọ ilé-ẹ̀kọ́ tí màa lọ tàbí iṣẹ́ tí máa yàn láàyò? 

Ìbéèrè tío dára l'èyí. Adùn ibẹ̀ nìyí: T'íwọ bá ń tẹ̀lé Jésù tío sì ń bá àwọn ènìyàn mímọ́ ṣe, Èmi Mímọ́ máa tọ́ ṣíṣe ìpinnu rẹ. 

O lè ma ṣiyèméjì lóri ilé-ẹ̀kọ́ gíga méjì tí ó dára, láìmọ èyí tí Ọlọ́run fẹ́ kí o lọ nínú méjèèjì. Jẹ́kí a padà wo àṣẹ pàtàkì méjì tí Jésù ṣòro rẹ̀: Ìfẹ́ Ọlọ́run àti ìfẹ́ ọmọlàkejì. Ǹjẹ́ o lè fẹ́ràn Ọlọ́run àti ọmọlàkejì rẹ ni ilé-ẹ̀kọ́ gíga méjèèjì bí? Tí ìdáhùn bá jẹ́ bẹ́ẹ̀ni, o kò nílò láti d'ara rẹ láàmú. Ọlọ́run lè lòọ́ níbi méjèèjì.

Nípa ìpinnu fún ètò ọjọ́-ọ̀la wa, Ọlọ́run lè má fún wa ní ìdáhùn “bẹ́ẹ̀ni” tàbí “bẹ́ẹ̀ kọ́”. Èyí lè fa ìpòrúru-ọkàn, ṣùgbọ́n ànfàní wà níbẹ̀ nígbà tí a bá mu yé ọ wípé ètò Ọlọ́run fún ayéè rẹ ní ìṣe pẹ̀lú ẹni t'íwọ yóò dà ju ohun tí ìwọ ìṣe. 

Ǹjẹ́ èyí wá túmọ̀ sí wípé a lè ṣe ohunkóhun tí a bá fẹ́ àti gbé ìgbé ayé tó wùn wá? Kò ríbẹ̀ o! A lè má ní ànfàní láti mọ ètò Ọlọ́run ni gbogbo ìgbà, ṣùgbọ́n a lè rìn ní ipasẹ̀ Ọlọ́run ni gbogbo ìgbà. Kíni èyí túmọ̀ sí? Ìtumọ̀ rẹ ni wípé bí a kò tilẹ̀ mọ ohun tíò kàn láyé wa, a lè tẹ̀síwájú nínú ìgbọràn sì ìpè Ọlọ́run ní àsìkò yìí. Èyí túmọ̀ sí títẹ̀lé, gbígbé ayé òtítọ́, ìgbọràn pẹ̀lú ìbọ̀wọ̀ fún òbí àti àwọn adarí, àti fí-féràn gbogbo ènìyàn tí Ọlọ́run bá mú wa pàdé. 

Ohun tó dùn jù níbẹ̀: Tí a bá tẹ̀lé Kristi, Yóò fún wa ní ọgbọ́n nípasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́. (Kọ́ríńtì Kínní 2:12-13) Yóò sọ èrò wa di titun (Róòmù 12:2) pẹ̀lú ìfojúsùn lórí àwọn ǹkan tíó tọ̀. Nígbà tí a bá wà ní sàkání àwọn ọlọ́gbọ́n (Òwe 13:20), àwọn pẹ̀lú yóò ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe ìpinnu rere. Ọ̀nà kan tí ó tún fi lè rí ọgbọ́n gbà ní nípasẹ̀ àdúrà. Kódà, Jákọ́bù 1:5 sọ wípé tí àwa bá bèrè fún ọgbọ́n lọ́dọ̀ Ọlọ́run, Yóò fi fún wa!  

Nípa Ìpèsè yìí

God’s Plan For Your Life

Kíni ètò Olúwa fún ayéè rẹ? Èyí jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìbéèrè tí a maá ń bèrè gẹ́gẹ́ bíi ọmọ-lẹ́yìn-Kristi. Ṣùgbọ́n, tí a bá ma jẹ olóòótọ́, ìrònú wa nípa ètò Olúwa fún ayé wa lè lágbára ju ọgbọ́n orí wa lọ. Nínú ètò Bíbélì ọlọ́jọ́-mẹ́fà yìí, a ó kọ́ọ wípé ètò Olúwa kò le bí a ti lérò, ṣùgbọ́n ó dára ní gbogbo ọ̀nà ju bí a ti lérò

More

A fẹ́ dúpẹ́ lọ́wọ́ ẹgbẹ́ Switch, ẹ̀ka iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ìjọ Life.Church, fún ìpèsè ètò yìí. Fún àlàyé síwájú síi, jọ̀wọ́ lọ sí: www.life.church