“Ọwọ́ rẹ ni ó mọ mi, tí ó sì da mi. Síbẹ̀ ìwọ tún yípadà láti jẹ mí run. Èmi bẹ̀ ọ́ rántí pé ìwọ ti mọ mí bí amọ̀; ìwọ yóò ha sì tún mú mi padà lọ sínú erùpẹ̀? Ìwọ kò ha ti tú mí dà jáde bí i wàrà, ìwọ kò sì mú mí dìpọ̀ bí i wàràǹkàṣì? Ìwọ sá ti fi àwọ̀ ẹran-ara wọ̀ mí, ìwọ sì fi egungun àti iṣan ṣọgbà yí mi ká. Ìwọ ti fún mi ní ẹ̀mí àti ojúrere, ìbẹ̀wò rẹ sì pa ọkàn mi mọ́. “Nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ sì ti fi pamọ́ nínú rẹ; èmi mọ̀ pé, èyí ń bẹ ní ọkàn rẹ. Bí mo bá ṣẹ̀, nígbà náà ni ìwọ yóò máa ṣọ́ mi ìwọ kì yóò sì dárí àìṣedéédéé mi jì. Bí mo bá ṣe ẹni búburú, ègbé ni fún mi! Bí mo bá sì ṣe ẹni rere, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì le gbe orí mi sókè. Èmi dààmú, mo si wo ìpọ́njú mi. Bí mo bá gbé orí mi ga. Ìwọ ń dẹ mí kiri bi i kìnnìún; àti pẹ̀lú, ìwọ a sì fi ara rẹ hàn fún mi ní ìyànjú. Ìwọ sì tún mun àwọn ẹlẹ́rìí rẹ dìde sí mi di ọ̀tún, Ìwọ sì sọ ìrunú rẹ di púpọ̀ sí mi; Àwọn ogun rẹ si dìde sinmi bi igbe omi Òkun. “Nítorí kí ni ìwọ ṣe mú mi jáde láti inú wá? Háà! Èmi ìbá kúkú ti kú, ojúkójú kì bá tí rí mi. Tí kò bá le jẹ́ pé èmi wà láààyè, À bá ti gbé mi láti inú lọ isà òkú. Ọjọ́ mi kò ha kúrú bí? Rárá! Dáwọ́ dúró, kí ó sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ mi. Nítorí kí èmi lè ni ayọ̀ ní ìṣẹ́jú kan. Kí èmi kí ó tó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà sẹ́yìn mọ́, Àní si ilẹ̀ òkùnkùn àti òjìji ikú. Ilẹ̀ òkùnkùn bí òkùnkùn tìkára rẹ̀, Àti ti òjìji ikú àti rúdurùdu, Níbi tí ìmọ́lẹ̀ dàbí òkùnkùn.”
Kà Jobu 10
Feti si Jobu 10
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Jobu 10:8-22
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò