2 Samuẹli 7:1-5

2 Samuẹli 7:1-5 BMYO

Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí OLúWA sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.” Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé OLúWA wà pẹ̀lú rẹ.” Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ OLúWA tọ Natani wá pé, “Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni OLúWA wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.