OLUWA, má fi ibinu bá mi wí! Má sì fi ìrúnú jẹ mí níyà! Nítorí pé ọfà rẹ ti wọ̀ mí lára, ọwọ́ rẹ sì ti bà mí. Kò sí ibìkan tí ó gbádùn ní gbogbo ara mi nítorí ibinu rẹ; kò sì sí alaafia ninu gbogbo egungun mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti bò mí lórí mọ́lẹ̀; ó rìn mí mọ́lẹ̀ bí ẹrù ńlá tí ó wúwo jù fún mi. Ọgbẹ́ mi ń kẹ̀, ó sì ń rùn, nítorí ìwà òmùgọ̀ mi, Ìbànújẹ́ dorí mi kodò patapata, mo sì ń ṣọ̀fọ̀ kiri tọ̀sán-tòru. Gbogbo ẹ̀gbẹ́ mi ń gbóná fòò, kò sí ibìkan tí ó gbádùn lára mi. Àárẹ̀ mú mi patapata, gbogbo ara sì wó mi; mò ń kérora nítorí ẹ̀dùn ọkàn mi. OLUWA, gbogbo ìfẹ́ ọkàn mi ni o mọ̀, ìmí ẹ̀dùn mi kò sì pamọ́ fún ọ. Àyà mi ń lù pì pì pì, ó rẹ̀ mí láti inú wá; ojú mi sì ti di bàìbàì.
Kà ORIN DAFIDI 38
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 38:1-10
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò