Ó rọ̀ ọ́ pẹlu ọpọlọpọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, ó fi ọ̀rọ̀ dídùn mú un. Lẹsẹkẹsẹ, ọmọkunrin náà bẹ̀rẹ̀ sí tẹ̀lé e, bíi mààlúù tí wọn ń fà lọ pa, tabi bí àgbọ̀nrín tí ó tẹsẹ̀ bọ tàkúté, títí tí ọfà fi wọ̀ ọ́ ninu bí ẹyẹ tí ń yára bọ́ sinu okùn, láì mọ̀ pé ó lè ṣe ikú pa òun. Nisinsinyii, ẹ fetí sílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ farabalẹ̀ gbọ́ nǹkan tí mò ń sọ. Ẹ má jẹ́ kí ọkàn yín lọ sọ́dọ̀ irú obinrin bẹ́ẹ̀, ẹ má ṣèèṣì yà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ọ̀pọ̀ ni àwọn tí ó ti sọ di ẹni ilẹ̀, ọpọlọpọ àwọn alágbára ni ó ti ṣe ikú pa. Ọ̀nà isà òkú tààrà ni ilé rẹ̀, ilé rẹ̀ ni ọ̀nà àbùjá sí ìparun.
Kà ÌWÉ ÒWE 7
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ÌWÉ ÒWE 7:21-27
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò