Ìwọ ọ̀lẹ, tọ èèrùn lọ, ṣàkíyèsí ìṣe rẹ̀, kí o sì kọ́gbọ́n. Ẹ̀dá tí kò ní olórí, tabi alabojuto, tabi aláṣẹ sibẹsibẹ, a máa tọ́jú oúnjẹ rẹ̀ ní àkókò ẹ̀ẹ̀rùn; a sì máa kó oúnjẹ jọ, ní àkókò ìkórè. O óo ti sùn pẹ́ tó, ìwọ ọ̀lẹ? Ìgbà wo ni o óo tají lójú oorun? Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi, yóo jẹ́ kí òṣì dé bá ọ, bí ọlọ́ṣà dé bá eniyan. Àìní yóo sì dé bá ọ bíi jagunjagun dé báni. Eniyan lásán, ìkà eniyan, a máa rìn káàkiri, a máa sọ̀rọ̀ àrékérekè, bí ó ti ń ṣẹ́jú, bẹ́ẹ̀ ni ó ń jansẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ó sì ń fi ìka ṣe àpèjúwe. Ó ń fi inú burúkú pète ibi, ó sì ń fi ojoojumọ dá ìjà sílẹ̀, nítorí náà, ibi yóo dé bá a lójijì, yóo parun kíá láìsí àtúnṣe.
Kà ÌWÉ ÒWE 6
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ÌWÉ ÒWE 6:6-15
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò