Ẹni tí ó kọ etí dídi sí òfin Ọlọrun, adura rẹ̀ pàápàá yóo di ìríra sí Ọlọ́run. Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi, yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀, ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire. Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀, ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀. Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀, ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́. Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere, ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo, ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu. Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka, dàbí kinniun tí ń bú ramúramù, tabi ẹranko beari tí inú ń bí. Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye, ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.
Kà ÌWÉ ÒWE 28
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ÌWÉ ÒWE 28:9-16
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò