ÌWÉ ÒWE 22:7-16

ÌWÉ ÒWE 22:7-16 YCE

Ọlọ́rọ̀ máa ń jọba lé talaka lórí, ẹni tí ó lọ yá owó sì ni ẹrú ẹni tí ó yá a lówó. Ẹni tí ó bá gbin aiṣododo yóo kórè ìdààmú, pàṣán ibinu rẹ̀ yóo sì parun. Olójú àánú yóo rí ibukun gbà, nítorí pé ó ń fún talaka ninu oúnjẹ rẹ̀. Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀, asọ̀ ati èébú yóo sì dópin. Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́, tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́. Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́, ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po. Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta! Yóo pa mí jẹ lójú pópó!” Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá, ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀. Ìwà agídí dì sí ọkàn ọmọde, ṣugbọn pàṣán ìbáwí níí lé e jáde. Ẹni tí ó ni talaka lára kí ó lè ní ohun ìní pupọ, tabi tí ó ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ yóo pada di talaka.