NỌMBA 6:23-27

NỌMBA 6:23-27 YCE

kí ó sọ fún Aaroni ati àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Báyìí ni ẹ óo máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. ‘Kí OLUWA bukun yín, kí ó sì pa yín mọ́. Kí OLUWA mú kí ojú rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí yín lára, kí ó sì ṣàánú fún yín. Kí OLUWA bojúwò yín, kí ó sì fún yín ní alaafia.’ “Bẹ́ẹ̀ ni wọn óo fi orúkọ mi súre fún àwọn ọmọ Israẹli, n óo sì bukun wọn.”