“Nítorí náà, n kò ní dákẹ́; n óo sọ ìrora ọkàn mi; n óo tú ìbànújẹ́ mi jáde. Ṣé òkun ni mí ni, tabi erinmi, tí ẹ fi yan olùṣọ́ tì mí? Nígbà tí mo wí pé, ‘Ibùsùn mi yóo tù mí lára, ìjókòó mi yóo sì mú kí ara tù mí ninu ìráhùn mi’. Nígbà náà ni ẹ̀yin tún wá fi àlá yín dẹ́rù bà mí, tí ẹ sì fi ìran pá mi láyà, kí n lè fara mọ́ ọn pé ó sàn kí á lọ́ mi lọ́rùn pa, kí n sì lè yan ikú dípò pé kí n wà láàyè. Ayé sú mi, n kò ní wà láàyè títí lae. Ẹ fi mí sílẹ̀, nítorí ọjọ́ ayé mi dàbí èémí lásán. Kí ni eniyan jẹ́, tí o fi gbé e ga, tí o sì fi ń náání rẹ̀; tí ò ń bẹ̀ ẹ́ wò láràárọ̀, tí o sì ń dán an wò nígbà gbogbo? Yóo ti pẹ́ tó kí ẹ tó mójú kúrò lára mi? Kí ẹ tó fi mí lọ́rùn sílẹ̀ kí n rí ààyè dá itọ́ mì? Bí mo bá ṣẹ̀, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ṣẹ̀ yín, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń ṣọ́ mi? Kí ló dé tí ẹ fi dójú lé mi, tí mo di ẹrù lọ́rùn yín? Kí ló dé tí ẹ kò lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí kí ẹ sì fojú fo àìdára mi? Láìpẹ́ n óo lọ sinu ibojì. Ẹ óo wá mi, ṣugbọn n kò ní sí mọ́.”
Kà JOBU 7
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 7:11-21
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò