JOBU 23:13-17

JOBU 23:13-17 YCE

“Ṣugbọn Ọlọrun kìí yipada, kò sí ẹni tí ó lè yí i lọ́kàn pada. Ohun tí ó bá fẹ́ gan-an ni yóo ṣe. Yóo ṣe ohun tí ó ti pinnu láti ṣe fún mi ní àṣeyọrí, ati ọpọlọpọ nǹkan bẹ́ẹ̀ yòókù tí ó tún ní lọ́kàn láti ṣe fún mi. Ìdí nìyí tí ẹ̀rù fi bà mí níwájú rẹ̀, tí mo bá ro nǹkan wọnyi, jìnnìjìnnì rẹ̀ a bò mí. Ọlọrun ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi, Olodumare ti dẹ́rùbà mí. Nítorí pé òkùnkùn yí mi ká, òkùnkùn biribiri sì ṣú bò mí lójú.