Jobu dáhùn pé, “Ẹ fetí sí ọ̀rọ̀ mi dáradára, kí ẹ sì jẹ́ kí ó jẹ́ ìtùnú fun yín. Ẹ farabalẹ̀, kí ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, lẹ́yìn náà, ẹ lè máa fi mí ṣẹ̀sín ǹṣó. Ṣé eniyan ni mò ń bá rojọ́ ni? Kí ló dé tí n óo fi mú sùúrù? Ẹ wò mí, kí ẹnu yà yín, kí ẹ sì fọwọ́ bo ẹnu. Nígbà tí mo ro ohun tí ó dé bá mi, ẹ̀rù bà mí, mo sì wárìrì. Kí ló dé tí eniyan burúkú fi wà láàyè, tí ó di arúgbó, tí ó sì di alágbára? Àwọn ọmọ wọn ati arọmọdọmọ wọn di eniyan pataki pataki lójú ayé wọn. Kò sí ìfòyà ninu ilé wọn, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọrun kò jẹ wọ́n níyà. Àwọn mààlúù wọn ń gùn, wọ́n sì ń bímọ ní àbíyè. Wọn a máa kó àwọn ọmọ wọn jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa ṣe àríyá. Wọn a máa fi aro, ìlù, ati fèrè kọrin, wọn a sì máa yọ̀ sí ohùn dùùrù. Wọn a máa gbé inú ọlá, wọn a sì máa kú ikú alaafia. Wọ́n ń sọ fún Ọlọrun pé, ‘Fi wá sílẹ̀! A kò fẹ́ mọ òfin rẹ. Ta ni Olodumare, tí a óo fi máa sìn ín? Èrè wo ni ó wà níbẹ̀ fún wa bí à ń gbadura sí i?’ Wọ́n rò pé ìkáwọ́ wọn ni ọlà wọn wà, nítèmi n kò lè tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn eniyan burúkú.
Kà JOBU 21
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 21:1-16
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò