Jobu dáhùn pé: “Láìsí àní àní, ẹ̀yin ni agbẹnusọ gbogbo eniyan, bí ẹ bá jáde láyé, ọgbọ́n kan kò tún ní sí láyé mọ́. Bí ẹ ti ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà ní, ẹ kò sàn jù mí lọ. Ta ni kò mọ irú nǹkan, tí ẹ̀ ń sọ yìí? Mo wá di ẹlẹ́yà lójú àwọn ọ̀rẹ́ mi, èmi tí mò ń ké pe Ọlọrun, tí ó sì ń dá mi lóhùn; èmi tí mo jẹ́ olódodo ati aláìlẹ́bi, mo wá di ẹlẹ́yà. Lójú ẹni tí ara tù, ìṣòro kì í báni láìnídìí. Lójú rẹ̀, ẹni tí ó bá ṣìṣe ni ìṣòro wà fún. Àwọn olè ń gbé ilé wọn ní alaafia, àwọn tí wọn ń mú Ọlọrun bínú wà ní àìléwu, àwọn tí ó jẹ́ pé agbára wọn ni Ọlọrun wọn. “Ṣugbọn, bèèrè lọ́wọ́ àwọn ẹranko, wọn óo sì kọ́ ọ, bi àwọn ẹyẹ, wọn yóo sì sọ fún ọ; tabi kí o bi àwọn koríko, wọn yóo sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóo sì ṣe àlàyé fún ọ. Ta ni kò mọ̀ ninu gbogbo wọn pé OLUWA ló ṣe èyí? Ọwọ́ rẹ̀ ni ìyè gbogbo ẹ̀dá wà, ati ẹ̀mí gbogbo eniyan. Ṣebí etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, ahọ́n a sì máa tọ́ oúnjẹ wò? “Àgbà ló ni ọgbọ́n, àwọn ogbó tí wọ́n ti pẹ́ láyé ni wọ́n ni òye.
Kà JOBU 12
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 12:1-12
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò