“Ayé sú mi, nítorí náà n kò ní dákẹ́ ìráhùn; n óo sọ̀rọ̀ pẹlu ìbànújẹ́ ọkàn. N óo sọ fún Ọlọrun pé kí ó má dá mi lẹ́bi; kí ó sì jẹ́ kí n mọ ìdí tí ó fi ń bá mi jà. Ṣé ohun tí ó dára ni, Ọlọrun pé kí o máa ni eniyan lára, kí o kórìíra iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, kí o sì fẹ́ràn ète ẹni ibi? Ǹjẹ́ ojú rẹ dàbí ti eniyan? Ǹjẹ́ a máa rí nǹkan bí eniyan ṣe rí i? Ǹjẹ́ bí ọjọ́ ti eniyan ni ọjọ́ rẹ rí? Ǹjẹ́ ọdún rẹ rí bíi ti eniyan? Tí o fi wá ń wádìí àṣìṣe mi, tí o sì ń tanná wá ẹ̀ṣẹ̀ mi? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o mọ̀ pé n kò lẹ́bi, ati pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà mí lọ́wọ́ rẹ.
Kà JOBU 10
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOBU 10:1-7
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò