AISAYA 28:1-15

AISAYA 28:1-15 YCE

Adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí Efuraimu gbé! Ẹwà ògo rẹ̀ tí ń ṣá bí ìtànná náà gbé! Ìlú tí ó wà ní òkè àfonífojì dáradára, ohun àmúyangàn fún àwọn tí ó mutí yó. Wò ó! OLUWA ní ẹnìkan, tí ó lágbára bí ẹ̀fúùfù líle, ati bí ìjì apanirun, bí afẹ́fẹ́ òjò tí ó lágbára tí àgbàrá rẹ̀ ṣàn kọjá bèbè; ẹni náà yóo bì wọ́n lulẹ̀. Ẹsẹ̀ ni yóo fi tẹ adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí ilẹ̀ Efuraimu. Ògo rẹ̀ tí ń ṣá bí òdòdó tí ó wà ní òkè àfonífojì dáradára, yóo dàbí àkọ́so èso ọ̀pọ̀tọ́, tí ó pọ́n ṣáájú ìgbà ìkórè. Ẹni tó bá rí i yóo sáré sí i, yóo ká a, yóo sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo jẹ́ adé ògo ati adé ẹwà, fún àwọn tí ó kù ninu àwọn eniyan rẹ̀. Yóo jẹ́ ẹ̀mí ìdájọ́ ẹ̀tọ́ fún adájọ́ tí ó jókòó lórí ìtẹ́ ìdájọ́, yóo jẹ́ agbára fún àwọn tí ó ń lé ogun sẹ́yìn lẹ́nu ibodè. Ọtí waini ń ti àwọn wọnyi, ọtí líle ń mú wọn ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n. Ọtí líle ń ti alufaa ati wolii, ọtí waini kò jẹ́ kí wọ́n mọ ohun tí wọ́n ń ṣe mọ́. Ọtí líle ń mú wọn ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n; wọ́n ń ríran èké, wọ́n ń dájọ́ irọ́. Nítorí èébì kún orí gbogbo tabili oúnjẹ, gbogbo ilẹ̀ sì kún fún ìdọ̀tí Wọ́n ń sọ pé, “Ta ni yóo kọ́ lọ́gbọ́n? Ta sì ni yóo jíṣẹ́ náà fún? Ṣé àwọn tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gbọyàn lẹ́nu wọn, àbí àwọn tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ já lẹ́nu ọmú? Nítorí pé gbogbo rẹ̀ tòfin-tòfin ni, èyí òfin, tọ̀hún ìlànà. Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún.” Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn àjèjì tí èdè wọn yàtọ̀ ni OLUWA yóo lò láti bá àwọn eniyan wọnyi sọ̀rọ̀. Àwọn tí ó ti wí fún pé: Ìsinmi nìyí, ẹ fún àwọn tí àárẹ̀ mú ní ìsinmi; ìtura nìyí. Sibẹsibẹ wọ́n kọ̀, wọn kò gbọ́. Nítorí náà ọ̀rọ̀ OLUWA sí wọn yóo jẹ́ tòfin-tòfin, èyí òfin tọ̀hún ìlànà. Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún, kí wọ́n baà lè lọ ṣubú sẹ́yìn kí wọ́n sì fọ́ wẹ́wẹ́; kí á lè dẹ tàkúté sílẹ̀ fún wọn, kí ọwọ́ lè tẹ̀ wọ́n. Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí, ẹ̀yin oníyẹ̀yẹ́ eniyan, tí ẹ̀ ń ṣe àkóso àwọn eniyan wọnyi ní Jerusalẹmu. Nítorí ẹ wí pé: “A ti bá ikú dá majẹmu, a sì ti bá ibojì ṣe àdéhùn. Nígbà tí jamba bá ń bọ̀, kò ní dé ọ̀dọ̀ wa; nítorí a ti fi irọ́ ṣe ibi ìsádi wa, a sì ti fi èké ṣe ibi ààbò.”