KRONIKA KINNI 24
24
Iṣẹ́ Àwọn Alufaa
1Bí a ṣe pín àwọn ọmọ Aaroni nìyí: Aaroni ní ọmọkunrin mẹrin: Nadabu, Abihu, Eleasari ati Itamari. 2Nadabu ati Abihu kú ṣáájú baba wọn láì bí ọmọ kankan. Nítorí náà, Eleasari, ati Itamari di alufaa. 3Pẹlu ìrànlọ́wọ́ Sadoku ọmọ Eleasari ati Ahimeleki ọmọ Itamari, Dafidi pín àwọn ọmọ Aaroni sí ẹgbẹẹgbẹ́ gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ tí wọn ń ṣe ninu iṣẹ́ ìsìn.#Lef 10:1-2
4Àwọn tí wọ́n jẹ́ baálé baálé pọ̀ ninu àwọn ọmọ Eleasari ju ti Itamari lọ, nítorí náà, wọ́n pín àwọn ọmọ Eleasari sí abẹ́ àwọn baálé baálé mẹrindinlogun, wọ́n sì pín àwọn ọmọ Itamari sí abẹ́ àwọn baálé baálé mẹjọ. Bí wọ́n ṣe pín wọn kò sì fì sí ibìkan nítorí pé 5gègé ni wọ́n ṣẹ́ tí wọ́n fi yàn wọ́n, nítorí pé, bí àwọn alámòójútó ìsìn ati alámòójútó iṣẹ́ ilé Ọlọrun ṣe wà ninu àwọn ìran Eleasari, bẹ́ẹ̀ náà ni wọ́n wà ninu ti Itamari. 6Ṣemaaya, akọ̀wé, ọmọ Netaneli, láti inú ẹ̀yà Lefi, ni ó kọ orúkọ wọn sílẹ̀ níwájú ọba ati àwọn ìjòyè, ati Sadoku, alufaa, ati Ahimeleki, ọmọ Abiatari, ati àwọn baálé baálé ninu ìdílé àwọn alufaa, ati ti àwọn ọmọ Lefi. Bí wọ́n bá ti mú ọ̀kan láti inú ìran Eleasari, wọn á sì tún mú ọ̀kan láti ìran Itamari.
7Gègé tí wọ́n kọ́kọ́ ṣẹ́ mú Jehoiaribu, ekeji mú Jedaaya. Gègé sì mú àwọn yòókù wọnyi tẹ̀léra wọn báyìí: 8Harimu, Seorimu; 9Malikija, Mijamini; 10Hakosi, Abija, 11Jeṣua, Ṣekanaya; 12Eliaṣibu, Jakimu, 13Hupa, Jeṣebeabu; 14Biliga, Imeri, 15Hesiri, Hapisesi; 16Petahaya, Jehesikeli, 17Jakini, Gamuli; 18Delaaya, Maasaya.
19Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n óo ṣe tẹ̀léra wọn níbi iṣẹ́ ṣíṣe ninu ilé OLUWA, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí Aaroni, baba wọn, ti là sílẹ̀ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí OLUWA Ọlọrun pa fún Israẹli.
Orúkọ Àwọn Ọmọ Lefi
20Àwọn olórí ninu ìdílé àwọn ọmọ Lefi yòókù nìwọ̀nyí: Ṣubaeli láti inú ìdílé Amramu,
Jedeaya láti inú ìdílé Ṣubaeli.
21Iṣaya tí ó jẹ́ olórí láti inú ìdílé Rehabaya,
22Ṣelomiti láti inú ìdílé Iṣari, Jahati láti inú ìdílé Ṣelomiti.
23Àwọn ọmọ Heburoni jẹ́ mẹrin: Jeraya ni olórí wọn, bí àwọn yòókù wọn ṣe tẹ̀léra nìyí: Amaraya, Jahasieli ati Jekameamu.
24Mika láti inú ìdílé Usieli, Ṣamiri láti inú ìdílé Mika.
25Iṣaya ni arakunrin Mika. Sakaraya láti inú ìdílé Iṣaya.
26Mahili ati Muṣi láti inú ìdílé Merari. 27Àwọn ọmọ Merari láti inú ìdílé Jaasaya ni Beno ati Ṣohamu, Sakuri ati Ibiri. 28Eleasari láti inú ìdílé Mahili, Eleasari kò bí ọmọkunrin kankan. 29Jerameeli ọmọ Kiṣi, láti ìdílé Kiṣi. 30Muṣi ní ọmọkunrin mẹta: Mahili, Ederi, ati Jerimotu. Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ Lefi nìyí, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
31Àwọn olórí ìdílé náà ṣẹ́ gègé gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Aaroni, àwọn arakunrin wọn ti ṣe, níwájú ọba Dafidi, ati Sadoku, ati Ahimeleki, pẹlu àwọn olórí ninu ìdílé alufaa ati ti àwọn ọmọ Lefi.
Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:
KRONIKA KINNI 24: YCE
Ìsàmì-sí
Pín
Daako

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀
Bible Society of Nigeria © 1900/2010
KRONIKA KINNI 24
24
Iṣẹ́ Àwọn Alufaa
1Bí a ṣe pín àwọn ọmọ Aaroni nìyí: Aaroni ní ọmọkunrin mẹrin: Nadabu, Abihu, Eleasari ati Itamari. 2Nadabu ati Abihu kú ṣáájú baba wọn láì bí ọmọ kankan. Nítorí náà, Eleasari, ati Itamari di alufaa. 3Pẹlu ìrànlọ́wọ́ Sadoku ọmọ Eleasari ati Ahimeleki ọmọ Itamari, Dafidi pín àwọn ọmọ Aaroni sí ẹgbẹẹgbẹ́ gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ tí wọn ń ṣe ninu iṣẹ́ ìsìn.#Lef 10:1-2
4Àwọn tí wọ́n jẹ́ baálé baálé pọ̀ ninu àwọn ọmọ Eleasari ju ti Itamari lọ, nítorí náà, wọ́n pín àwọn ọmọ Eleasari sí abẹ́ àwọn baálé baálé mẹrindinlogun, wọ́n sì pín àwọn ọmọ Itamari sí abẹ́ àwọn baálé baálé mẹjọ. Bí wọ́n ṣe pín wọn kò sì fì sí ibìkan nítorí pé 5gègé ni wọ́n ṣẹ́ tí wọ́n fi yàn wọ́n, nítorí pé, bí àwọn alámòójútó ìsìn ati alámòójútó iṣẹ́ ilé Ọlọrun ṣe wà ninu àwọn ìran Eleasari, bẹ́ẹ̀ náà ni wọ́n wà ninu ti Itamari. 6Ṣemaaya, akọ̀wé, ọmọ Netaneli, láti inú ẹ̀yà Lefi, ni ó kọ orúkọ wọn sílẹ̀ níwájú ọba ati àwọn ìjòyè, ati Sadoku, alufaa, ati Ahimeleki, ọmọ Abiatari, ati àwọn baálé baálé ninu ìdílé àwọn alufaa, ati ti àwọn ọmọ Lefi. Bí wọ́n bá ti mú ọ̀kan láti inú ìran Eleasari, wọn á sì tún mú ọ̀kan láti ìran Itamari.
7Gègé tí wọ́n kọ́kọ́ ṣẹ́ mú Jehoiaribu, ekeji mú Jedaaya. Gègé sì mú àwọn yòókù wọnyi tẹ̀léra wọn báyìí: 8Harimu, Seorimu; 9Malikija, Mijamini; 10Hakosi, Abija, 11Jeṣua, Ṣekanaya; 12Eliaṣibu, Jakimu, 13Hupa, Jeṣebeabu; 14Biliga, Imeri, 15Hesiri, Hapisesi; 16Petahaya, Jehesikeli, 17Jakini, Gamuli; 18Delaaya, Maasaya.
19Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n óo ṣe tẹ̀léra wọn níbi iṣẹ́ ṣíṣe ninu ilé OLUWA, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí Aaroni, baba wọn, ti là sílẹ̀ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí OLUWA Ọlọrun pa fún Israẹli.
Orúkọ Àwọn Ọmọ Lefi
20Àwọn olórí ninu ìdílé àwọn ọmọ Lefi yòókù nìwọ̀nyí: Ṣubaeli láti inú ìdílé Amramu,
Jedeaya láti inú ìdílé Ṣubaeli.
21Iṣaya tí ó jẹ́ olórí láti inú ìdílé Rehabaya,
22Ṣelomiti láti inú ìdílé Iṣari, Jahati láti inú ìdílé Ṣelomiti.
23Àwọn ọmọ Heburoni jẹ́ mẹrin: Jeraya ni olórí wọn, bí àwọn yòókù wọn ṣe tẹ̀léra nìyí: Amaraya, Jahasieli ati Jekameamu.
24Mika láti inú ìdílé Usieli, Ṣamiri láti inú ìdílé Mika.
25Iṣaya ni arakunrin Mika. Sakaraya láti inú ìdílé Iṣaya.
26Mahili ati Muṣi láti inú ìdílé Merari. 27Àwọn ọmọ Merari láti inú ìdílé Jaasaya ni Beno ati Ṣohamu, Sakuri ati Ibiri. 28Eleasari láti inú ìdílé Mahili, Eleasari kò bí ọmọkunrin kankan. 29Jerameeli ọmọ Kiṣi, láti ìdílé Kiṣi. 30Muṣi ní ọmọkunrin mẹta: Mahili, Ederi, ati Jerimotu. Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ Lefi nìyí, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
31Àwọn olórí ìdílé náà ṣẹ́ gègé gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Aaroni, àwọn arakunrin wọn ti ṣe, níwájú ọba Dafidi, ati Sadoku, ati Ahimeleki, pẹlu àwọn olórí ninu ìdílé alufaa ati ti àwọn ọmọ Lefi.
Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:
:
Ìsàmì-sí
Pín
Daako

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀
Bible Society of Nigeria © 1900/2010