Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Iṣe Apo 2:43

Ìtọ́sọ́nà Àtọ̀runwá
Ojó Méje
Lójojúmọ́, a ma ńṣe àwọn àṣàyàn tó ń tọ́ ipa nínú ìtàn ìgbésí ayé wa. Báwo ni ìtàn ìgbésí ayé rẹ yóò ti rí tí o bá ṣe àwọn àṣàyàn tó dára? Nínú Ètò Bíbélì Ìtọ́sọ́nà Àtọ̀runwá, gbajú-gbajà ònkọ̀wé New York Times àti Olùṣọ́àgùntàn àgbà ní ìjọ Life.Church, Craig Groeschel, máa gbà ọ́ níyànjú pẹ̀lú àwọn ìlànà méje tí a fà jáde látinú ìwé Ìtọ́sọ́nà Àtọ̀runwá fún ìrànlọ́wọ́ láti ṣe àwárí ọgbọ́n Ọlọ́run fún àwọn ìpinnu tí à ńṣe lójojúmọ́. Ṣe àwárí àwọn ìtọ́ni ti ẹ̀mí tí o nílò láti gbé ìgbésí ayé tó bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run.

OHUN KAN
Ọjọ́ 7
A máa ri ohun tí ó túnmọ̀ sí láti gbé fún Jésù nínú ayé tí kò ní àfojúsùn. Ayé yìí n sáré, a sì ní ìròyìn ní àtẹ́lẹwọ́ wa ju bí a ṣe nílo lọ. Njẹ́ ìwà ayé tuntun yìí rèé? Báwo ni a ṣe lè rìn jẹ́jẹ́ ní ayé tí ó ń sáré yìí? Sáàmù 27:4 ní ìdáhùn – OHÙN KAN, pẹ̀lú Ps Andrew Cartledge.

Nígbàtí Ìgbàgbọ́ Bá Kùnà: Ọjọ́ Mẹ́wàá Nípa Wíwá Ọlọ́run Nínú Òjìji Iyèméjì
Ojó Méwàá
Ìlàkàkà pẹ̀lú ìgbàgbọ́ àti iyèméjì jẹ́ ohun tí ó lè jẹ́kí ènìyàn fẹ́ dáwà tàbí kí ó ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlòmíràn. Àwọn kàn ńdá jìyà láìjẹ́ kí enìkankan mọ̀, àwọn míràn kọ ìgbàgbọ́ sílẹ̀ lápapọ̀, wọ́n rò pé iyèméjì kò ní ìbámu pẹ̀lú ìgbàgbọ́. Dominic Done gbàgbọ́ wípé èyí jẹ́ àsìse àti oun tí ó bani lọ́kàn jẹ́. Ó lo Ìwé mímọ́ àti ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ láti jiyàn wípé bíbèèrè nípa ìgbàgbọ́ bójúmu àti wípé ó sábà máa ńjẹ́ ọ̀nà síhà ìgbàgbọ́ tí ó lọ́rọ̀ àti tí ó lárinrin. Yẹ ìgbàgbọ́ àti iyèméjì wò nínú ètò ọlọ́jọ́ mẹ́wàá yìí.