YouVersion Logo
Search Icon

LUKU 1

1
Ọ̀rọ̀ Iṣaaju sí Tiofilu
1Ọpọlọpọ eniyan ni wọ́n ti kọ ìròyìn lẹ́sẹẹsẹ, nípa ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ láàrin wa; 2àwọn tí nǹkan wọnyi ṣojú wọn, tí wọ́n sì sọ fún wa. 3Mo ti fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wádìí ohun gbogbo fínnífínní. Èmi náà wá pinnu láti kọ ìwé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ, ọlọ́lá jùlọ, Tiofilu, 4kí o lè mọ òtítọ́ àwọn nǹkan tí wọ́n kọ́ ọ.
Àsọtẹ́lẹ̀ Nípa Ìbí Johanu Onítẹ̀bọmi
5Ní àkókò Hẹrọdu, ọba Judia, alufaa kan wà tí ń jẹ́ Sakaraya, ní ìdílé Abiya. Orúkọ iyawo rẹ̀ ni Elisabẹti, láti inú ìdílé Aaroni. #1Kron 24:10 6Àwọn mejeeji ń rìn déédé níwájú Ọlọrun, wọ́n ń pa gbogbo àwọn àṣẹ ati ìlànà Oluwa mọ́ láì kùnà. 7Ṣugbọn wọn kò ní ọmọ, nítorí pé Elisabẹti yàgàn. Àwọn mejeeji ni wọ́n sì ti di arúgbó.
8Nígbà tí ó yá, ó kan ìpín àwọn Sakaraya láti wá ṣe iṣẹ́ alufaa níwájú Ọlọrun ninu Tẹmpili. 9Gẹ́gẹ́ bí àṣà àwọn alufaa, Sakaraya ni ìbò mú láti sun turari ninu iyàrá Tẹmpili Oluwa. 10Gbogbo àwọn eniyan ń gbadura lóde ní àkókò tí ó ń sun turari. 11Angẹli Oluwa kan bá yọ sí i, ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún pẹpẹ turari. 12Nígbà tí Sakaraya rí i, ó ta gìrì, ẹ̀rù bà á. 13Ṣugbọn angẹli náà sọ fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sakaraya, nítorí pé adura rẹ ti gbà. Elisabẹti iyawo rẹ yóo bí ọmọkunrin kan fún ọ, o óo pe orúkọ rẹ̀ ní Johanu. 14Ayọ̀ yóo kún ọkàn rẹ. Ọpọlọpọ eniyan ni yóo bá ọ yọ̀ nígbà tí ẹ bá bí ọmọ náà. 15Ọmọ náà yóo jẹ́ ẹni ńlá níwájú Oluwa. Kò gbọdọ̀ mu ọtíkọ́tí, ìbáà jẹ́ líle tabi èyí tí kò le. Yóo kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ láti ìgbà tí ó bá tí wà ninu ìyá rẹ̀; #Nọm 6:3 16ọpọlọpọ àwọn ọmọ Israẹli ni yóo sì yipada sí Oluwa Ọlọrun wọn. 17Òun ni yóo ṣáájú Oluwa pẹlu ẹ̀mí Elija ati agbára rẹ̀. Yóo mú kí àwọn baba wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹlu àwọn ọmọ wọn. Yóo yí àwọn alágídí ọkàn pada sí ọ̀nà rere. Yóo sọ àwọn eniyan di yíyẹ lọ́dọ̀ Oluwa.” #Mal 4:5-6; Sir 48:10-11
18Sakaraya bi angẹli náà pé, “Báwo ni n óo ti ṣe mọ̀? Nítorí pé mo ti di arúgbó; iyawo mi alára náà sì ti di àgbàlagbà.”
19Angẹli náà dá a lóhùn pé, “Geburẹli ni orúkọ mi, èmi ni mo máa ń dúró níwájú Ọlọrun. Ọlọrun ló rán mi láti bá ọ sọ̀rọ̀, ati láti sọ nǹkan ayọ̀ yìí fún ọ. #Dan 8:16; 9:21; Tob 12:15 20Nítorí pé ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́, o óo ya odi, o kò ní lè sọ̀rọ̀ títí ọjọ́ tí gbogbo nǹkan wọnyi yóo fi ṣẹlẹ̀. Gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ yìí yóo ṣẹ nígbà tí ó bá yá.”
21Àwọn eniyan ti ń retí Sakaraya. Ẹnu yà wọ́n pé ó pẹ́ ninu iyàrá Tẹmpili. 22Nígbà tí ó jáde, kò lè bá wọn sọ̀rọ̀. Wọ́n sì mọ̀ pé ó ti rí ìran ninu iyàrá Tẹmpili ni. Ó yadi, ọwọ́ ni ó fi ń ṣe àpèjúwe fún wọn.
23Nígbà tí ó parí àkókò tí yóo fi ṣiṣẹ́ alufaa ninu Tẹmpili, ó pada lọ sí ilé rẹ̀. 24Lẹ́yìn náà, Elisabẹti lóyún. Ó bá fi ara pamọ́ fún oṣù marun-un. Ó ní, 25“Oluwa ni ó ṣe èyí fún mi. Ó ti fi ojú àánú wò mí, ó sì ti mú ohun tí ó jẹ́ ẹ̀gàn fún mi lójú eniyan kúrò.”
Àsọtẹ́lẹ̀ Nípa Ìbí Jesu
26Ní oṣù kẹfa, Ọlọrun rán angẹli Geburẹli lọ sí ìlú kan ní Galili tí wọn ń pè ní Nasarẹti. 27Ọlọrun rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wundia kan tí ó jẹ́ iyawo àfẹ́sọ́nà ọkunrin kan tí ń jẹ́ Josẹfu, ti ìdílé Dafidi. Wundia náà ń jẹ́ Maria. #Mat 1:18 28Angẹli náà wọlé tọ Maria lọ, ó kí i, ó ní “Alaafia ni fún ọ! Ìwọ ẹni tí Ọlọrun kọjú sí ṣe ní oore, Oluwa wà pẹlu rẹ.”
29Nígbà tí Maria gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ara rẹ̀ kò balẹ̀, ó ń rò lọ́kàn rẹ̀ pé, irú kíkí wo nìyí? 30Angẹli náà sọ fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí o ti bá ojurere Ọlọrun pàdé. 31O óo lóyún, o óo sì bí ọmọkunrin kan, Jesu ni o óo pe orúkọ rẹ̀. #Mat 1:21 32Eniyan ńlá ni yóo jẹ́. Ọmọ Ọ̀gá Ògo ni a óo máa pè é. Oluwa Ọlọrun yóo fún un ní ìtẹ́ Dafidi, baba rẹ̀. 33Yóo jọba lórí ìdílé Jakọbu títí lae, ìjọba rẹ̀ kò ní lópin.” #2 Sam 7:12, 13, 16; Ais 9:7
34Maria bá bi angẹli náà pé, “Báwo ni yóo ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí n kò tíì mọ ọkunrin?”
35Angẹli náà dá a lóhùn pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóo tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá Ògo yóo ṣíji bò ọ́. Nítorí náà Ọmọ Mímọ́ Ọlọrun ni a óo máa pe ọmọ tí ìwọ óo bí. 36Ati pé Elisabẹti, ìbátan rẹ náà ti lóyún ọmọkunrin kan ní ìgbà ogbó rẹ̀. Ẹni tí wọ́n ti ń pè ní àgàn rí sì ti di aboyún oṣù mẹfa. 37Nítorí kò sí ohun tí ó ṣòro fún Ọlọrun.” #Jẹn 18:14
38Maria bá dáhùn pé, “Iranṣẹ Oluwa ni mí. Kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà bá fi í sílẹ̀ lọ.
Maria Lọ Bẹ Elisabẹti Wò
39Lẹ́yìn náà, Maria múra pẹlu ìwàǹwára, ó lọ sí ìlú Judia kan tí ó wà ní agbègbè orí òkè. 40Ó wọ inú ilé Sakaraya, ó bá kí Elisabẹti. 41Bí Elisabẹti ti gbọ́ ohùn Maria, bẹ́ẹ̀ ni ọlẹ̀ sọ ninu rẹ̀; Elisabẹti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́. 42Ó kígbe sókè, ó ní, “Ibukun Ọlọrun wà lórí rẹ pupọ láàrin àwọn obinrin. Ibukun Ọlọrun sì wà lórí ọmọ inú rẹ. #Judt 13:18 43Mo ṣe ṣe oríire tó báyìí, tí ìyá Oluwa mi fi wá sọ́dọ̀ mi? 44Nítorí bí mo ti gbọ́ ohùn rẹ nígbà tí o kí mi, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ inú mi sọ nítorí ó láyọ̀. 45Ayọ̀ ń bẹ fún ọ nítorí o gba ohun tí Oluwa ti sọ gbọ́, pé yóo ṣẹ.”
Maria Kọ Orin Ìyìn
46Nígbà náà ni Maria sọ pé,
“Ọkàn mi gbé Oluwa ga,
47ẹ̀mí mi yọ̀ sí Ọlọrun, Olùgbàlà mi,
48nítorí ó ti bojúwo ipò ìrẹ̀lẹ̀ iranṣẹbinrin rẹ̀.
Wò ó! Láti ìgbà yìí lọ
gbogbo ìran ni yóo máa pè mí ní olóríire. #1 Sam 1:11
49Nítorí Olodumare ti ṣe ohun ńlá fún mi,
Mímọ́ ni orúkọ rẹ̀;
50àánú rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran
fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
51Ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fi agbára rẹ̀ hàn,
ó tú àwọn tí ó gbéraga ninu ọkàn wọn ká.
52Ó yọ àwọn ìjòyè kúrò lórí oyè,
ó gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ga. #Job 5:11; 12:9; Sir 10:14
53Ó fi oúnjẹ tí ó dára bọ́ àwọn tí ebi ń pa,
ó mú àwọn ọlọ́rọ̀ jáde lọ́wọ́ òfo.
54Ó ran Israẹli ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́
nígbà tí ó ranti àánú rẹ̀,
55gẹ́gẹ́ bí ìlérí tí ó ti ṣe fún àwọn baba wa:
fún Abrahamu ati fún ìdílé rẹ̀ títí lae.” #Jẹn 17:7 #1 Sam 2:1-10
56Maria dúró lọ́dọ̀ Elisabẹti tó bíi oṣù mẹta, ó bá pada lọ sí ilé rẹ̀.
Ìbí Johanu Onítẹ̀bọmi
57Nígbà tí àkókò Elisabẹti tó tí yóo bí, ó bí ọmọkunrin kan. 58Àwọn aládùúgbò rẹ̀ ati àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ̀ gbọ́ pé Oluwa ti ṣàánú pupọ fún un, wọ́n wá bá a yọ̀.
59Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹjọ, wọ́n wá láti kọ́ ọmọ náà ní ilà-abẹ́. Wọ́n fẹ́ sọ ọ́ ní Sakaraya, bí orúkọ baba rẹ̀. #Lef 12:3 60Ṣugbọn ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Rárá o! Johanu ni a óo máa pè é.”
61Wọ́n sọ fún un pé, “Kò sí ẹnìkan ninu àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ tí ó ń jẹ́ orúkọ yìí.” 62Wọ́n wá ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀ pé báwo ni ó fẹ́ kí á máa pe ọmọ náà.
63Ó bá bèèrè fún nǹkan ìkọ̀wé, ó kọ ọ́ pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu ya gbogbo eniyan. 64Lẹsẹkẹsẹ ohùn Sakaraya bá là, okùn ahọ́n rẹ̀ tú, ó bá ń sọ̀rọ̀, ó ń yin Ọlọrun. 65Ẹ̀rù ńlá ba gbogbo àwọn aládùúgbò wọn. Ìròyìn tàn ká gbogbo agbègbè olókè Judia, wọ́n ń sọ ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀. 66Gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ń da ọ̀rọ̀ náà rò ninu ọkàn wọn, wọ́n ń sọ pé, “Irú ọmọ wo ni èyí yóo jẹ́?” Nítorí ọwọ́ Oluwa wà lára rẹ̀.
Sakaraya Sọ Àsọtẹ́lẹ̀
67Sakaraya, baba ọmọ náà, kún fún Ẹ̀mí Mímọ́. Ó bá sọ àsọtẹ́lẹ̀ pé,
68Kí á yin Oluwa Ọlọrun Israẹli
nítorí ó ti mú ìrànlọ́wọ́ wá fún àwọn eniyan rẹ̀,
ó sì ti dá wọn nídè.
69Ó ti gbé Olùgbàlà dìde fún wa
ní ìdílé Dafidi, iranṣẹ rẹ̀;
70gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ láti ẹnu àwọn wolii rẹ̀ mímọ́,
láti ọjọ́ pípẹ́;
71pé yóo gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa
ati lọ́wọ́ gbogbo àwọn tí ó kórìíra wa;
72pé yóo fi àánú bá àwọn baba wa lò,
ati pé yóo ranti majẹmu rẹ̀ mímọ́
73gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún Abrahamu baba wa,
74pé yóo gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,
ati pé yóo fún wa ní anfaani láti máa sìn ín láì fòyà,
75pẹlu ọkàn kan ati pẹlu òdodo
níwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé wa.
76“Ìwọ, ọmọ mi,
wolii Ọ̀gá Ògo ni a óo máa pè ọ́,
nítorí ìwọ ni yóo ṣáájú Oluwa láti palẹ̀ mọ́ dè é, #Mal 3:1
77láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn eniyan rẹ̀,
nípa ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
78nítorí àánú Ọlọrun wa,
nípa èyí tí oòrùn ìgbàlà fi ràn lé wa lórí láti òkè wá,
79láti tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn tí ó wà ní òkùnkùn
ati àwọn tí ó jókòó níbi òjìji ikú,
láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà alaafia.” #Ais 9:2
80Ọmọ náà ń dàgbà, ó sì ń lágbára sí i lára ati lẹ́mìí. Ilẹ̀ aṣálẹ̀ ni ó ń gbé títí di àkókò tí ó fara han àwọn eniyan Israẹli.

Currently Selected:

LUKU 1: YCE

Highlight

Share

Copy

None

Want to have your highlights saved across all your devices? Sign up or sign in

YouVersion uses cookies to personalize your experience. By using our website, you accept our use of cookies as described in our Privacy Policy