Job 6:1-13
Job 6:1-13 Bibeli Mimọ (YBCV)
JOBU si dahùn o si wipe, A! a ba le iwọ̀n ibinujẹ mi ninu òṣuwọn, ki a si le igbe ọ̀fọ mi le ori òṣuwọn ṣọkan pọ̀! Njẹ nisisiyi, iba wuwo jù iyanrin okun lọ: nitorina li ọ̀rọ mi ṣe ntàse. Nitoripe ọfa Olodumare wọ̀ mi ninu, oró eyiti ọkàn mi mu; ipaiya-ẹ̀ru Ọlorun dotì mi. Kẹtẹkẹtẹ ìgbẹ a ma dún, nigbati o ba ni koriko, tabi ọdá-malu a ma dún sori ijẹ rẹ̀? A le jẹ ohun ti kò li adùn li aini iyọ̀, tabi adùn wà ninu funfun ẹyin? Ohun ti ọkàn mi kọ̀ lati tọ́, on li o dàbi onjẹ mi ti kò ni adùn. A! emi iba lè ri iberè mi gbà; ati pe, ki Ọlọrun le fi ohun ti emi ṣafẹri fun mi. Ani, Ọlọrun iba jẹ pa mi run, ti on iba jẹ ṣiwọ rẹ̀ ki o si ké mi kuro. Nigbana ni emi iba ni itunú sibẹ, ani emi iba mu ọkàn mi le ninu ibinujẹ mi ti kò da ni si: nitori emi kò fi ọ̀rọ Ẹni Mimọ́ nì sin ri. Kili agbara mi ti emi o fi dabá? ki si li opin mi ti emi o fi fà ẹmi mi gùn? Agbara mi iṣe agbara okuta bi, tabi ẹran ara mi iṣe idẹ? Iranlọwọ mi kò ha wà ninu mi: ọgbọn ha ti salọ kuro lọdọ mi bi?
Job 6:1-13 Yoruba Bible (YCE)
Jobu bá dáhùn pé, “Bí ó bá ṣeéṣe láti wọn ìbànújẹ́ mi, tí a bá sì le gbé ìdààmú mi lé orí ìwọ̀n, ìbá wúwo ju yanrìn etí òkun lọ. Ìdí nìyí tí mo fi ń fi ìtara sọ̀rọ̀. Ọfà Olodumare wọ̀ mí lára, oró rẹ̀ sì mú mi. Ọlọrun kó ìpayà bá mi. Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó a máa ké tí ó bá rí koríko jẹ? Àbí mààlúù a máa dún tí ó bá ń wo oúnjẹ rẹ̀ nílẹ̀? Ǹjẹ́ ohun tí kò dùn ṣe é jẹ láì fi iyọ̀ sí i? Tabi, adùn wo ní ń bẹ ninu funfun ẹyin? Irú oúnjẹ bẹ́ẹ̀ kì í wù mí í jẹ, Ìríra ni jíjẹ rẹ̀ jẹ́ fún mi. “Ìbá ti dára tó, kí Ọlọrun mú ìbéèrè mi ṣẹ, kí ó fún mi ní ohun tí ọkàn mi ń fẹ́. Àní, kí ó wó mi mọ́lẹ̀, kí ó mú mi, kí ó pa mí dànù. Yóo jẹ́ ìtùnú fún mi; n óo sì láyọ̀ ninu ọpọlọpọ ìrora, nítorí pé n kò sẹ́ ọ̀rọ̀ Ẹni Mímọ́. Agbára wo ni mo ní, tí mo fi lè tún máa wà láàyè? Kí sì ni ìrètí mi, tí n óo fi tún máa ní sùúrù? Agbára mi ha rí bí ti òkúta bí? Àbí ẹran ara mi jẹ́ idẹ? Nítòótọ́, n kò ní agbára mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní olùrànlọ́wọ́.
Job 6:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Jobu sì dáhùn ó si wí pé: “Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òṣùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òṣùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀! Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn Òkun lọ: nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí. Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀? A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin? Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀. “Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi. Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò. Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí. “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù? Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ? Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?