Job 27:11-23
Job 27:11-23 Bibeli Mimọ (YBCV)
Emi o kọ́ nyin li ẹkọ́ niti ọwọ Ọlọrun: eyi ti mbẹ lọdọ Olodumare li emi kì yio fi pamọ. Kiyesi i, gbogbo nyin li o ti ri i, nitori kili ẹnyin ṣe jasi asan pọ̀ bẹ̃? Eyi ni ipín enia buburu lọdọ Ọlọrun, ati ogún awọn aninilara, ti nwọn o gbà lọwọ Olodumare. Bi awọn ọmọ rẹ̀ ba di pupọ̀, fun idà ni, awọn ọmọ-ọmọ rẹ̀ kì yio yo fun onjẹ. Awọn ti o kù ninu tirẹ̀ li a o sinkú ninu ajakalẹ àrun: awọn opó rẹ̀ kì yio si sọkún. Bi o tilẹ kó fàdaka jọ bi erupẹ, ti o si da aṣọ jọ bi amọ̀. Ki o ma dá a, ṣugbọn awọn olõtọ ni yio lò o; awọn alaiṣẹ̀ ni yio si pin fadaka na. On kọ́ ile rẹ̀ bi kòkoro aṣọ, ati bi agọbukà ti oluṣọ pa. Ọlọrọ̀ yio dubulẹ, ṣugbọn on kì o tùn ṣe bẹ̃ mọ́, o ṣiju rẹ̀, on kò sì si. Ẹ̀ru nla bà a bi omi ṣiṣan, ẹ̀fufu nla ji i gbe lọ li oru. Ẹfufu ila-õrùn gbe e lọ, on si lọ; ati bi iji nla o si fà a kuro ni ipo rẹ̀. Nitoripe Olodumare yio kọlù u, kì o sì dasi; on iba yọ̀ lati sá kuro li ọwọ rẹ̀. Awọn enia yio si ṣapẹ si i lori, nwọn o si ṣe ṣiọ si i kuro ni ipò rẹ̀.
Job 27:11-23 Yoruba Bible (YCE)
“N óo kọ yín ní ìmọ̀ agbára Ọlọ́run; n kò sì ní fi ohun tíí ṣe ti Olodumare pamọ́. Wò ó! Gbogbo yín ni ẹ ti fojú yín rí i, kí ló wá dé tí gbogbo yín fí ń sọ ìsọkúsọ?” “Ìpín ẹni ibi láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun nìyí, òun ni ogún tí àwọn aninilára ń rí gbà lọ́dọ̀ Olodumare: Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá ń pọ̀ sí i, kí ogun baà lè pa wọ́n ni, oúnjẹ kò sì ní ká wọn lẹ́nu. Àwọn ọmọ tí wọn bá gbẹ̀yìn rẹ̀, àjàkálẹ̀ àrùn ni yóo pa wọ́n, àwọn opó wọn kò sì ní ṣọ̀fọ̀ wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ń kó fadaka jọ bí erùpẹ̀, tí ó sì to aṣọ jọ bí amọ̀; olódodo ni yóo wọ aṣọ tí ó bá kó jọ, àwọn aláìṣẹ̀ ni yóo pín fadaka rẹ̀. Ilé tí ó kọ́ dàbí òwú aláǹtakùn, àní bí àgọ́ àwọn tí wọn ń ṣọ́nà. A ti máa wọlé sùn pẹlu ọrọ̀ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn kò ní rí bẹ́ẹ̀ fún un mọ́. Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo ọrọ̀ rẹ̀ yóo ti fò lọ. Ìwárìrì á bò ó mọ́lẹ̀ bí ìkún omi, ní alẹ́, ìjì líle á gbé e lọ. Afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn á fẹ́ ẹ sókè, á sì gbé e lọ, á gbá a kúrò ní ipò rẹ̀. Á dìgbò lù ú láìṣàánú rẹ̀, á sá lọ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀. Ọlọrun á pàtẹ́wọ́ lé e lórí, á sì pòṣé sí i láti ibi tí ó wà.
Job 27:11-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
“Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run: ọ̀nà tí ń bẹ lọ́dọ̀ Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́. Kíyèsi i, gbogbo yín ni ó ti rí i; kín ni ìdí ọ̀rọ̀ asán yín? “Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àti ogún àwọn aninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmarè: Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fún idà ni; àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ. Àwọn tí ó kù nínú tirẹ̀ ni a ó sìnkú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn: àwọn opó rẹ̀ kì yóò sì sọkún fún wọn. Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀, tí ó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀; àwọn ohun tí ó tò jọ àwọn olóòtítọ́ ni yóò lò ó; àwọn aláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀. Òun kọ́ ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kòkòrò aṣọ, àti bí ahéré tí olùṣọ́ kọ́. Ọlọ́rọ̀ yóò dùbúlẹ̀, ṣùgbọ́n òun kì yóò túnṣe bẹ́ẹ̀ mọ́; Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo rẹ̀ a lọ Ẹ̀rù ńlá bà á bí omi ṣíṣàn; ẹ̀fúùfù ńlá jí gbé lọ ní òru. Ẹ̀fúùfù ìlà-oòrùn gbé e lọ, òun sì lọ; àti bí ìjì ńlá ó sì fà á kúrò ní ipò rẹ̀. Nítorí pé Olódùmarè yóò kọlù ú, kì yóò sì dá sí; òun ìbá yọ̀ láti sá kúrò ní ọwọ́ rẹ̀. Àwọn ènìyàn yóò sì ṣápẹ́ sí i lórí, wọn yóò sì ṣe síọ̀ sí i kúrò ní ipò rẹ̀.”