II. Sam 19:1-7
II. Sam 19:1-7 Bibeli Mimọ (YBCV)
A si rò fun Joabu pe, Wõ, ọba nsọkun, o si ngbawẹ fun Absalomu. Iṣẹgun ijọ na si di awẹ̀ fun gbogbo awọn enia na, nitori awọn enia na gbọ́ ni ijọ na bi inu ọba ti bajẹ nitori ọmọ rẹ̀. Awọn enia na si yọ́ lọ si ilu ni ijọ na gẹgẹ bi awọn enia ti a dojuti a ma yọ́ lọ nigbati nwọn nsá loju ijà. Ọba si bo oju rẹ̀, ọba si kigbe li ohùn rara pe, A! ọmọ mi Absalomu, Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi! Joabu si wọ inu ile tọ ọba lọ, o si wipe, Iwọ dojuti gbogbo awọn iranṣẹ rẹ loni, awọn ti o gbà ẹmi rẹ là loni, ati ẹmi awọn ọmọkunrin rẹ, ati ti awọn ọmọbinrin rẹ, ati ẹmi awọn aya rẹ, ati ẹmi awọn obinrin rẹ. Nitoripe iwọ fẹ awọn ọta rẹ, iwọ si korira awọn ọrẹ rẹ. Nitoriti iwọ wi loni pe, Iwọ kò nani awọn ọmọ ọba, tabi awọn iranṣẹ: emi si ri loni pe, ibaṣepe Absalomu wà lãye, ki gbogbo wa si kú loni, njẹ iba dùnmọ ọ gidigidi. Si dide nisisiyi, lọ, ki o si sọ̀rọ itùnú fun awọn iranṣẹ rẹ: nitoripe emi fi Oluwa bura, bi iwọ kò ba lọ, ẹnikan kì yio ba ọ duro li alẹ yi: ati eyini yio si buru fun ọ jù gbogbo ibi ti oju rẹ ti nri lati igbà ewe rẹ wá titi o fi di isisiyi.
II. Sam 19:1-7 Yoruba Bible (YCE)
Àwọn kan lọ sọ fún Joabu pé, ọba ń sọkún, ó sì ń ṣọ̀fọ̀ Absalomu. Nítorí náà, ìṣẹ́gun ọjọ́ náà pada di ìbànújẹ́ fún gbogbo àwọn eniyan; nítorí wọ́n gbọ́ pé ọba ń ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀. Àwọn ọmọ ogun náà yọ́ wọ ìlú jẹ́ẹ́, bí ẹni pé wọ́n sá lójú ogun, tí ìtìjú sì mú wọn. Ọba dọwọ́ bojú, ó ń sọkún, ó sì ń kígbe sókè pé, “Ọmọ mi! Absalomu, ọmọ mi! Absalomu, ọmọ mi!” Joabu bá wọlé tọ ọba lọ, ó wí fún un pé, “O ti dójúti àwọn ọmọ ogun rẹ lónìí, àwọn tí wọ́n gba ẹ̀mí rẹ là, ati ẹ̀mí àwọn ọmọ rẹ, ati ti àwọn aya rẹ, ati àwọn obinrin rẹ; nítorí pé o fẹ́ràn àwọn tí wọ́n kórìíra rẹ, o sì kórìíra àwọn tí wọ́n fẹ́ràn rẹ. O ti fihàn gbangba pé, àwọn ọ̀gágun ati ọmọ ogun rẹ kò jẹ́ nǹkankan lójú rẹ. Mo ti rí i gbangba lónìí pé, ìbá dùn mọ́ ọ ninu, bí gbogbo wa tilẹ̀ kú, tí Absalomu sì wà láàyè. Yára dìde, kí o lọ tu àwọn ọmọ ogun ninu; nítorí pé mo fi OLUWA búra pé, bí o kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, kò ní ku ẹnìkan ninu wọn pẹlu rẹ ní òwúrọ̀ ọ̀la. Èyí yóo wá burú ju gbogbo ibi tí ó ti bá ọ láti ìgbà èwe rẹ títí di òní lọ.”
II. Sam 19:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
A sì rò fún Joabu pe, “Wò ó, ọba ń sọkún, ó sì ń gbààwẹ̀ fún Absalomu.” Ìṣẹ́gun ọjọ́ náà sì di àwẹ̀ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, nítorí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ní ọjọ́ náà bí inú ọba ti bàjẹ́ nítorí ọmọ rẹ̀. Àwọn ènìyàn náà sì yọ́ lọ sí ìlú ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí àwọn bí ènìyàn tí a dójútì ṣe máa ń yọ́ lọ nígbà tí wọ́n bá sá lójú ìjà. Ọba sì bo ojú rẹ̀, ọba sì kígbe ní ohùn rara pé, “Á à! Ọmọ mi Absalomu! Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi!” Joabu sì wọ inú ilé tọ ọba lọ, ó sì wí pé, “Ìwọ dójúti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ lónìí, àwọn tí ó gba ẹ̀mí rẹ̀ là lónìí, àti ẹ̀mí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti ti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, àti àwọn aya rẹ̀, àti ẹ̀mí àwọn obìnrin rẹ. Nítorí pé ìwọ fẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ sì kórìíra àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Nítorí tí ìwọ wí lónìí pé, Ìwọ kò náání àwọn ọmọ ọba tàbí àwọn ìránṣẹ́; èmi sì rí lónìí pé, ìbá ṣe pé Absalomu wà láààyè, kí gbogbo wa sì kú lónìí, ǹjẹ́ ìbá dùn mọ́ ọ gidigidi. Sì dìde nísinsin yìí, lọ, kí o sì sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ: nítorí pé èmi fi OLúWA búra, bí ìwọ kò bá lọ, ẹnìkan kì yóò bá ọ dúró ni alẹ́ yìí: èyí ni yóò sì burú fún ọ ju gbogbo ibi tí ojú rẹ ti ń rí láti ìgbà èwe rẹ wá títí ó fi di ìsinsin yìí.”