I. Sam 12:18-25
I. Sam 12:18-25 Bibeli Mimọ (YBCV)
Samueli si kepe Oluwa, Oluwa si ran ãra ati ojò ni ọjọ na: gbogbo enia si bẹru Oluwa pupọ ati Samueli. Gbogbo enia si wi fun Samueli pe, Gbadura si Oluwa Ọlọrun rẹ fun awọn iranṣẹ rẹ, ki awa ki o má ba kú: nitori ti awa ti fi buburu yi kun gbogbo ẹṣẹ wa ni bibere ọba fun ara wa. Samueli si wi fun awọn enia na pe, Ẹ má bẹ̀ru: ẹnyin ti ṣe gbogbo buburu yi: sibẹ ẹ má pada lẹhin Oluwa, ẹ ma fi gbogbo ọkàn nyin sin Oluwa. Ẹ máṣe yipada; nitori yio jasi itẹle ohun asan lẹhin, eyi ti kì yio ni ere; bẹ̃ni kì yio si gbanila; nitori asan ni nwọn. Nitoriti Oluwa kì yio kọ̀ awọn enia rẹ̀ silẹ nitori orukọ rẹ̀ nla: nitoripe o wu Oluwa lati fi nyin ṣe enia rẹ̀. Pẹlupẹlu bi o ṣe ti emi ni, ki a má ri i pe emi si dẹṣẹ̀ si Oluwa ni didẹkun gbadura fun nyin: emi o si kọ́ nyin li ọ̀na rere ati titọ. Ṣugbọn ẹ bẹ̀ru Oluwa, ki ẹ si fi gbogbo ọkàn nyin sin i lododo: njẹ, ẹ ronu ohun nlanla ti o ṣe fun nyin. Ṣugbọn bi ẹnyin ba hu ìwa buburu sibẹ, ẹnyin o ṣegbé t'ẹnyin t'ọba nyin.
I. Sam 12:18-25 Yoruba Bible (YCE)
Samuẹli bá gbadura, ní ọjọ́ náà gan-an, OLUWA sán ààrá, ó sì rọ òjò. Ẹ̀rù OLUWA ati ti Samuẹli sì ba gbogbo àwọn eniyan náà. Wọ́n bá wí fún Samuẹli pé, “Gbadura sí OLUWA Ọlọrun rẹ fún wa, kí á má baà kú. Nítorí pé a mọ̀ nisinsinyii pé, yàtọ̀ fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí a ti dá tẹ́lẹ̀, ẹ̀ṣẹ̀ tún ni bíbèèrè tí a bèèrè fún ọba tún jẹ́ lọ́rùn wa.” Samuẹli dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ohun tí ẹ ṣe burú, sibẹsibẹ ẹ má ṣe yipada kúrò lọ́dọ̀ OLUWA, ṣugbọn ẹ máa sìn ín pẹlu gbogbo ọkàn yín. Ẹ má tẹ̀lé àwọn oriṣa; ohun asán tí kò lérè, tí kò sì lè gbani ni wọ́n. OLUWA kò ní ta eniyan rẹ̀ nù, nítorí orúkọ ńlá rẹ̀, nítorí pé ó wù ú láti ṣe yín ní eniyan rẹ̀. Ní tèmi, n kò ní ṣẹ̀, nípa aigbadura sí OLUWA fun yín. N óo sì máa kọ yín ní ohun tí ó dára láti máa ṣe ati ọ̀nà tí ó tọ́ fun yín láti máa rìn. Ẹ máa bẹ̀rù OLUWA, kí ẹ sì máa sìn ín pẹlu gbogbo ọkàn yín. Ẹ ranti àwọn nǹkan ńláńlá tí ó ti ṣe fun yín. Ṣugbọn bí ẹ bá tún ṣe nǹkan burúkú, yóo pa ẹ̀yin ati ọba yín run.”
I. Sam 12:18-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (BMYO)
Nígbà náà ni Samuẹli ké pe OLúWA, OLúWA sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù OLúWA àti Samuẹli púpọ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí OLúWA Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.” Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ OLúWA, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin OLúWA. Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n. Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ OLúWA kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú OLúWA dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀. Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí OLúWA nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́. Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù OLúWA, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín. Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”