Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú O. Daf 16:7

Gbogbo Ǹkan Tí Mo Nílò
Ọjọ́ Mẹ́ta
Ọlọ́run ti lọ ṣáájú wa ó sì ń pa wá mọ́ ní ọwọ́ ẹ̀yìn. Gbogbo ìdojúkọ wa ló ti yanjú. Gbogbo àlàfo ìdojúkọ ló sì ti dí pẹ̀lú. Ìpèníjà kò lè dé bá a lójijì. Ẹ̀kọ́ Àṣàrò Bíbélì ọlọ́jọ́-mẹ́ta yìí ma gbà ẹ́ ní ìyànjú nípa òtítọ́ wípé Ọlọ́run ni Olùpèsè ohun tó tọ́, àti èyí tó yẹ, fún ìgbésí ayé rẹ.

Gbígbọ́ lati Ọ̀run: Títẹ́ Etí S'ílẹ̀ Sí Olúwa Nínú Ìgbésí Ayé Ojoojúmọ́
Ọjọ marun
Olúwa wà láàyè, Ó sì ń ṣiṣẹ́ ní óde òní, Ó ń bá olúkúlùkù àwọn ọmọ Rẹ̀ s'ọ̀rọ̀ ní tààràtà. Àmọ́ ní ìgbà míràn, Ó máa ń ṣòro láti rí I àti láti gbọ́ Ọ. Nípa yíyànnàná ìtàn ìrìn àjò ọkùnrin kan láti ní òye ohùn Ọlọ́run ní ìgbèríko Nairobi, ìwọ yíó mọ bí ó ti rí láti gbọ́ àti láti tẹ̀lé E.

Ayọ̀ fún Ìrìnàjò náà: Wíwá Ìrètí ní Àárín Ìdánwò
Ọjọ́ Méje
A lè má rí i tàbí ní í l'érò ní ìgbà gbogbo, ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa ní ìgbà gbogbo... kódà ní ìgbà tí a bá ń la àwọn ìṣòro kọjá. Nínú ètò yìí, Amy LaRue Olùdarí Finding Hope ṣe àkọsílẹ̀ àtọkànwá nípa ìjàkadì ìdílé rẹ̀ pẹ̀lú ìwà bárakú àti bí ayọ̀ Ọlọ́run ṣe jẹyọ ní àwọn àkókò tí ó nira jùlọ.